< Jeremiah 17 >

1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
Le péché de Juda est écrit avec un style de fer, une pointe de diamant; il est gravé sur la table de leur cœur et aux cornes de leurs autels.
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
Comme ils pensent à leurs enfants, ainsi pensent-ils à leurs autels, et à leurs Aschères près des arbres verdoyants et sur les collines élevées.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
O ma montagne, qui es dans la campagne! je donnerai ton bien, tous tes trésors en pillage, et tes hauts lieux, à cause de tes péchés commis dans toutes tes limites.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Et tu auras, et par ta faute, à laisser là ton héritage que je te donnai; et je t'asservirai à tes ennemis dans un pays que tu ne connais pas, car vous avez allumé le feu de ma colère, et il brûlera toujours.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Ainsi parle l'Éternel: Maudit soit l'homme qui se confie dans l'homme, et qui prend la chair pour son appui, et dont le cœur déserte l'Éternel!
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Il est comme un homme nu dans un désert, et ne voit point le bonheur arriver; il habite les lieux brûlés du désert, une terre salée et inhabitée.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Béni soit l'homme qui se confie dans l'Éternel, et dont l'Éternel est la confiance!
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Il est comme un arbre planté près des eaux; il pousse ses racines vers le courant, et ne craint pas quand la chaleur vient, et son feuillage est vert, et dans l'année de sécheresse il n'est point inquiet, et il ne cesse de porter du fruit.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Rien n'est plus tortueux que le cœur, et il est méchant; qui peut le connaître?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Moi, l'Éternel, je sonde le cœur, j'éprouve les reins, et cela pour rendre à chacun selon ses voies, selon le fruit de ses œuvres.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Une perdrix qui couve des œufs qu'elle n'a point pondus, tel est l'homme qui se crée une richesse sans la droiture: à la moitié de ses jours il devra la quitter, et à sa fin il se trouvera être un insensé.
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Le lieu de mon Sanctuaire est un trône de gloire et de majesté dès le commencement.
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
Espoir d'Israël, ô Éternel, quiconque t'abandonne, sera confondu. – « Ceux qui me quittent, seront inscrits sur la poussière, car ils abandonnent la source des eaux vives, l'Éternel. »
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Guéris-moi, Éternel, et je serai guéri; sauve-moi, et je serai sauvé, car tu es ma gloire.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Voici, ils me disent: Où est la parole de l'Éternel? qu'elle se réalise donc!
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Et moi, je n'ai point évité de te suivre comme pasteur, et je n'ai point désiré le jour du malheur, tu le sais; ce qui est sorti de mes lèvres, est découvert à tes regards.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Ne sois point mon effroi, toi, mon refuge au jour du malheur.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Confonds mes persécuteurs, mais ne me confonds pas; atterre-les, mais ne m'atterre pas! Fais venir sur eux le jour du malheur, brise-les à coups redoublés!
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Ainsi me parla l'Éternel: Va, et te place à la porte des fils du peuple, par laquelle entrent et sortent les rois de Juda, et à toutes les portes de Jérusalem,
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
et dis-leur: Écoutez la parole de l'Éternel, rois de Juda, et tout Juda, et vous tous les habitants de Jérusalem, qui passez par ces portes!
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Ainsi parle l'Éternel: Prenez garde à vous pour l'amour de vos âmes, et ne portez point de fardeaux le jour du repos, et ne les faites pas passer par les portes de Jérusalem;
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
et ne transportez aucun fardeau hors de vos maisons le jour du repos, et ne faites aucune œuvre; mais sanctifiez le jour du repos, ainsi que je le prescrivis à vos pères.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Cependant ils n'obéirent pas, et ne prêtèrent pas l'oreille, mais roidirent leur col, pour ne point écouter et ne point recevoir la correction.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Mais si vous m'obéissez, dit l'Éternel, en ne portant point de fardeaux par les portes de cette ville le jour du repos, et si vous sanctifiez le jour du repos en ne faisant aucune œuvre ce jour-là, alors,
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
par les portes de cette ville entreront les rois et les princes assis sur le trône de David, montés sur des chars et des chevaux, eux et leurs princes, les hommes de Juda et les habitants de Jérusalem, et cette ville sera habitée éternellement,
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
et l'on viendra des villes de Juda, et des alentours de Jérusalem, et du pays de Benjamin et du Bas-Pays, et de la montagne et du Midi, offrir des holocaustes, des victimes, et des offrandes et de l'encens, et offrir des actions de grâces dans la maison de l'Éternel.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Mais si vous ne m'obéissez pas, en sanctifiant le jour du repos, et en ne portant aucun fardeau, et en n'entrant point dans les portes de Jérusalem le jour du repos, j'allumerai un feu aux portes de la ville, afin qu'il dévore les palais de Jérusalem et ne s'éteigne point.

< Jeremiah 17 >