< Jeremiah 17 >

1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
« Le péché de Juda est écrit avec une plume de fer, et avec la pointe d'un diamant. Elle est gravée sur la tablette de leur cœur, et sur les cornes de vos autels.
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
Même leurs enfants se souviennent de leurs autels et leurs mâts d'Ashérah près des arbres verts sur les hautes collines.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
Ma montagne dans le champ, Je donnerai vos biens et tous vos trésors en pillage, et tes hauts lieux, à cause du péché, dans tout ton territoire.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Vous, même de vous-mêmes, vous abandonnerez l'héritage que je vous ai donné. Je vous ferai servir vos ennemis dans un pays que vous ne connaissez pas, car tu as allumé dans ma colère un feu qui brûlera à jamais. »
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Yahvé dit: « Maudit soit l'homme qui se confie en l'homme, s'appuie sur la force de la chair, et dont le cœur s'éloigne de Yahvé.
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Car il sera comme un buisson dans le désert, et ne verront pas quand le bien arrive, mais habitera les lieux desséchés du désert, une terre salée inhabitée.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
« Heureux l'homme qui se confie en Yahvé, et dont la confiance est en Yahvé.
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Car il sera comme un arbre planté près des eaux, qui étend ses racines près de la rivière, et n'aura pas peur quand la chaleur viendra, mais sa feuille sera verte, et ne sera pas inquiété l'année de la sécheresse. Il ne cessera pas de donner des fruits.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Le cœur est trompeur par-dessus tout. et il est extrêmement corrompu. Qui peut le savoir?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
« Moi, Yahvé, je sonde l'esprit. J'essaie le cœur, de rendre à chacun selon ses voies, selon le fruit de ses actions. »
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Comme la perdrix qui s'assied sur des œufs qu'elle n'a pas pondus, ainsi est celui qui obtient des richesses, et non par droit. Au milieu de ses jours, ils le quitteront. A sa fin, il sera un imbécile.
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Un trône glorieux, placé en haut dès le commencement, est le lieu de notre sanctuaire.
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
Yahvé, l'espoir d'Israël, tous ceux qui t'abandonnent seront déçus. Ceux qui s'éloignent de moi seront inscrits sur la terre, parce qu'ils ont abandonné Yahvé, la source d'eau vive.
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Guéris-moi, Yahvé, et je serai guéri. Sauve-moi, et je serai sauvé; car tu es ma louange.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Voici, ils me demandent, « Où est la parole de Yahvé? Qu'il s'accomplisse maintenant. »
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Quant à moi, je ne me suis pas empressé d'être un berger après vous. Je n'ai pas désiré le jour malheureux. Tu sais. Ce qui est sorti de mes lèvres était devant ton visage.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Ne sois pas une terreur pour moi. Tu es mon refuge au jour du malheur.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Que ceux qui me persécutent soient déçus, mais ne me laisse pas être déçu. Qu'ils soient consternés, mais ne me laissez pas être consterné. Faites venir sur eux le jour du malheur, et les détruire doublement.
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Yahvé m'a dit ceci: « Va te tenir à la porte des enfants du peuple, par laquelle les rois de Juda entrent et par laquelle ils sortent, et à toutes les portes de Jérusalem.
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
Dis-leur: « Écoutez la parole de Yahvé, rois de Juda, tout Juda et tous les habitants de Jérusalem, qui entrez par ces portes:
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Yahvé dit: « Prenez garde, ne portez pas de fardeau le jour du sabbat, et ne le faites pas entrer par les portes de Jérusalem.
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
Ne portez pas de fardeau hors de vos maisons le jour du sabbat. Ne faites pas d'ouvrage, mais sanctifiez le jour du sabbat, comme je l'ai ordonné à vos pères.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Mais ils n'ont pas écouté. Ils n'ont pas prêté l'oreille, mais ils ont raidi leur cou, afin de ne pas entendre et de ne pas recevoir d'instruction.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Si vous m'écoutez attentivement, dit l'Éternel, vous ne ferez entrer aucun fardeau par les portes de cette ville le jour du sabbat, vous sanctifierez le jour du sabbat et vous ne ferez aucun ouvrage.
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
Alors entreront par les portes de cette ville des rois et des princes assis sur le trône de David, montés sur des chars et sur des chevaux, eux et leurs princes, les hommes de Juda et les habitants de Jérusalem, et cette ville subsistera à jamais.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Ils viendront des villes de Juda et des environs de Jérusalem, du pays de Benjamin, de la plaine, de la montagne et du Midi, apportant des holocaustes, des sacrifices, des offrandes, de l'encens et des sacrifices d'action de grâces à la maison de l'Éternel.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Mais si vous ne m'écoutez pas pour sanctifier le jour du sabbat, pour ne pas porter de fardeau et entrer aux portes de Jérusalem le jour du sabbat, j'allumerai un feu dans ses portes, et il dévorera les palais de Jérusalem. Il ne s'éteindra pas. »'"

< Jeremiah 17 >