< Jeremiah 17 >

1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
"Juudan synti on kirjoitettu rautapiirtimellä, timanttikärjellä, kaiverrettu heidän sydämensä tauluun ja teidän alttarienne sarviin,
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
ja niin heidän lapsensa muistavat alttarinsa ja asera-karsikkonsa viheriäin puitten vieressä, korkeilla kukkuloilla.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
Oman vuoreni, joka on kedolla, niin myös sinun tavarasi, kaikki sinun aarteesi ja sinun uhrikukkulasi minä annan ryöstettäviksi synnin tähden kaikkia rajojasi myöten.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Sinun on luovuttava perintöosastasi, jonka minä olen sinulle antanut; ja minä saatan sinut vihollistesi orjuuteen maassa, jota sinä et tunne. Sillä te olette sytyttäneet minun vihani tulen; se on palava iankaikkisesti.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Näin sanoo Herra: Kirottu on se mies, joka turvaa ihmisiin ja tekee lihan käsivarreksensa ja jonka sydän luopuu Herrasta.
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Hän jää alastomaksi arolle eikä näe mitään onnea tulevan; hän asuu poudan polttamissa paikoissa erämaassa, asumattomassa suolamaassa.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Siunattu on se mies, joka turvaa Herraan, jonka turvana Herra on.
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Hän on kuin veden partaalle istutettu puu, joka ojentaa juurensa puron puoleen; helteen tuloa se ei peljästy, vaan sen lehvä on vihanta, ei poutavuonnakaan sillä ole huolta, eikä se herkeä hedelmää tekemästä.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Petollinen on sydän ylitse kaiken ja pahanilkinen; kuka taitaa sen tuntea?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Minä, Herra, tutkin sydämen, koettelen munaskuut, ja annan jokaiselle hänen vaelluksensa mukaan, hänen töittensä hedelmän mukaan.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Peltokana, joka hautoo, mitä ei ole muninut, on se, joka hankkii rikkautta vääryydellä; päiviensä puolivälissä hänen täytyy se jättää, ja hänen loppunsa on houkan loppu."
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Kunnian valtaistuin, korkea ikiajoista, meidän pyhäkkömme paikka!
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
Israelin toivo, sinä Herra! Kaikki, jotka sinut hylkäävät, joutuvat häpeään. "Jotka minusta luopuvat, ne kirjoitetaan tomuun. Sillä he ovat hyljänneet elävän veden lähteen, Herran."
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Paranna minut, Herra, niin minä parannun, auta minua, niin olen autettu. Sillä sinä olet minun ylistykseni.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Katso, he sanovat minulle: "Missä on Herran sana? Toteutukoon se!"
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Mutta minä en ole vetäytynyt pois olemasta paimenena, sinua seuraamasta, enkä toivonut turmion päivää; sinä tiedät sen. Mitä minun huuliltani on lähtenyt, se on sinun kasvojesi edessä.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Älä tule minulle peljätykseksi, sinä, minun turvani onnettomuuden päivänä.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Joutukoot häpeään ne, jotka minua vainoavat, mutta älä anna minun häpeään tulla; peljästykööt he, mutta älä anna minun peljästyä. Tuota heille onnettomuuden päivä ja tuhoa heidät kaksinkertaisella tuholla.
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Näin sanoi Herra minulle: "Mene ja seiso Kansanportissa, josta Juudan kuninkaat tulevat ja josta he menevät, ja kaikissa Jerusalemin porteissa.
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
Ja sano heille: Kuulkaa Herran sana, te Juudan kuninkaat ja koko Juuda ja kaikki Jerusalemin asukkaat, jotka tulette näistä porteista.
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Näin sanoo Herra: Ottakaa itsestänne tarkka vaari, älkää sapatinpäivänä mitään kantamusta kantako älkääkä mitään tuoko Jerusalemin porteista.
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
Älkää viekö sapatinpäivänä mitään kantamusta taloistanne älkääkä tehkö mitään työtä, vaan pyhittäkää sapatinpäivä, niinkuin minä käskin teidän isienne tehdä.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Mutta he eivät kuulleet, eivät korvaansa kallistaneet, vaan olivat niskureita, niin etteivät kuulleet eivätkä ottaneet kuritusta varteen.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Jos kuulette minua, sanoo Herra, niin ettette tuo mitään kantamusta tämän kaupungin porteista sapatinpäivänä, vaan pyhitätte sapatinpäivän, niin ettette silloin tee mitään työtä,
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
niin tulee tämän kaupungin porteista sisälle, ajaen vaunuilla ja hevosilla, kuninkaita ja ruhtinaita, jotka istuvat Daavidin valtaistuimella, tulevat he ja heidän ruhtinaansa, Juudan miehet ja Jerusalemin asukkaat, ja tämä kaupunki on oleva asuttu iankaikkisesti.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Ja Juudan kaupungeista ja Jerusalemin ympäriltä, Benjaminin maasta ja Alankomaasta, Vuoristosta ja Etelämaasta tulee niitä, jotka tuovat polttouhreja ja teurasuhreja, ruokauhreja ja suitsutusuhreja, tuovat kiitosuhreja Herran huoneeseen.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Mutta jos ette kuule minua ettekä pyhitä sapatinpäivää, vaan kannatte kantamuksia ja kuljette Jerusalemin porteista sapatinpäivänä, niin minä sytytän tuleen sen portit, ja tuli on kuluttava Jerusalemin palatsit, eikä se ole sammuva."

< Jeremiah 17 >