< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Perwerdigarning sözi manga kélip mundaq déyildi: —
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
Sen ayal zatini emringge almaysen, shundaqla mushu zéminda oghul-qiz perzent tapmaysen.
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Chünki Perwerdigar bu yerde tughulghan oghul-qizlar, bu zéminda ularni tughqan anilar we ularni tughdurghan atilar toghrisida mundaq deydu: —
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
Ular elemlik késeller bilen ölidu; ular üchün héch matem tutulmaydu, ular kömülmeydu; ölükliri tézektek tupraq yüzide yatidu, ular qilich, qehetchilik bilen yep kétilidu; jesetliri asmandiki uchar-qanatlar we zémindiki haywanatlar üchün ozuq bolidu.
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Chünki Perwerdigar mundaq deydu: — Sen [Yeremiya], haza boluwatqan héchbir öyge kirme, yaki ölgenler üchün ah-zar kötürüsh yaki ökünüshke barma; chünki Men bu xelqtin xatirjemlikimni, méhir-muhebbitimni we rehimdilliklirimni élip tashlidim, — deydu Perwerdigar.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Ulughlardin tartip peslergiche bu zéminda ölidu; ular yerge kömülmeydu; héchkim ular üchün ah-zar kötürmeydu, yaki ularni dep, ya etlirini tilmaydu, ya chachlirini chüshürüwetmeydu;
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
ular qariliq tutqanlarni yoqlap, nan oshtumaydu, ölgenler üchün köngül sorimaydu; ata-anisi ölgenler üchün héchkim teselli qedehini sunmaydu.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
Sen bolsang el-yurt bilen bille yep-ichishke toy-bezme bolghan öygimu kirme;
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
chünki samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar, Israilning Xudasi mundaq deydu: — Mana, Men öz künliringlarda we öz köz aldinglarda, bu yerdin tamashining sadasini, shad-xuramliq sadasini we toyi boluwatqan yigit-qizning awazlirini toxtitimen.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
Shundaq boliduki, sen bu xelqqe bu sözlerning hemmisini éytqiningda, ular sendin: «Némishqa Perwerdigar mushundaq zor bir külpetni béshimizgha chüshürüshke békitken? Bizning qebihlikimiz zadi néme? Perwerdigar Xudayimiz aldida zadi sadir qilghan néme gunahimiz bardu?» — dep soraydu.
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Emdi sen ulargha mundaq deysen: — Chünki ata-bowiliringlar Mendin waz kechken, — deydu Perwerdigar, — hemde bashqa ilahlargha egiship ularning qulluqida bolghan, ulargha choqun’ghan; ular Mendin waz kechken, Tewrat-qanunumni héch tutmighan;
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
siler bolsanglar, ata-bowililiringlardin téximu better qilghansiler; mana, herbiringlar öz rezil könglidiki jahilliqning keynige kirip, Manga héch qulaq salmighansiler;
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Shunga Men silerni bu zémindin élip, siler yaki ata-bowiliringlar héch bilmeydighan bashqa bir zémin’gha tashlaymen; siler shu yerde kéche-kündüz bashqa ilahlarning qulluqida bolisiler; chünki Men silerge héch méhirni körsetmeymen.
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
Shunga mana, shu künler kéliduki, — deydu Perwerdigar, — «Israillarni Misir zéminidin qutquzup chiqarghan Perwerdigarning hayati bilen!» dégen qesem qaytidin ishlitilmeydu,
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
belki [shu künlerde] «Israillarni shimaliy zéminidin we Özi ularni heydigen barliq zéminlerdin qutquzup chiqarghan Perwerdigarning hayati bilen!» dep qesem ichilidu. Chünki Men ularni ata-bowilirigha teqdim qilghan zéminigha qayturimen.
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
Halbuki, mana hazir bolsa, Men nurghun béliqchilarni ewetip ularni tutquzushqa chaqirimen, — deydu Perwerdigar; — andin nurghun owchilarni ewetip ularni qoghlap owlashqa chaqirimen; ular ularni herbir taghdin, herbir égizliktin, qiya tashlarning ghar-qisilchaqliridin tépiwalidu.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Chünki közlirim ularning barliq yolliri üstide turidu; ular aldimda héch suqunalmidi, ularning qebihliki közlirimdin héch yoshurulmidi.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Lékin Men awwal ularning qebihlikini we gunahini béshigha hessilep qayturimen; chünki ular zéminimni yirginchlik nersilerning ölükliri bilen bulghighan, Méning mirasimni lenetlik nersiliri bilen toldurghan.
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
— I Perwerdigar, Sen méning küchüm we qorghinimsen, azab-oqubet künide bashpanahimsen. Eller bolsa yer yüzining chet-chetliridin yéninggha kélidu we: «Berheq, ata-bowilirimiz yalghanchiliq hem bimenilikke mirasxorluq qilghan; bu nersilerde héch payda yoqtur.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Insanlar öz-özige xudalarni yasiyalamdu?! Lékin yasighini Xuda emestur!» — deydu.
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
— Shunga, mana, Men bu qétim [bu rezil xelqqe] shuni obdan bildürimen, — ulargha Méning qolum we küch-qudritimni obdan bildürimen; shuning bilen ular Méning namimning Perwerdigar ikenlikini bilidu!

< Jeremiah 16 >