< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
Du skall icke taga dig någon hustru eller skaffa dig några söner och döttrar på denna plats.
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Ty så säger HERREN om de söner och döttrar som bliva I födda på denna plats, och om mödrarna som hava fött dem, och om fäderna som hava avlat dem i detta land:
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
Av svåra sjukdomar skola de dö; man skall icke hålla dödsklagan efter dem eller begrava dem, utan de skola bliva gödsel på marken. Och genom svärd och hunger skola de förgås, och deras döda kroppar skola bliva mat åt himmelens fåglar och markens djur. I
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Ty så säger HERREN: Du skall icke gå in i något sorgehus och icke begiva dig åstad för att hålla dödsklagan, ej heller ömka dem; ty jag har tagit bort min frid ifrån detta folk, säger HERREN, ja, min nåd och barmhärtighet.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Och både stora och små skola dö i detta land, utan att bliva begravna; och man skall icke hålla dödsklagan efter dem, och ingen skall för deras skull rista märken på sig eller raka sitt huvud.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
Man skall icke bryta bröd åt någon, för att trösta honom i sorgen efter en död, och icke giva någon tröstebägaren att dricka, när han har förlorat fader eller moder.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
Och i gästabudshus skall du icke heller gå in för att sitta med dem och äta och dricka.
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Ty så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Se, inför edra ögon, och medan I ännu leven, skall jag på denna plats göra slut på fröjderop och glädjerop, på rop för brudgum och rop för brud. I
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
När du nu förkunnar alla dessa ord för detta folk och de då fråga dig: "Varför har HERREN uttalat över oss all denna stora olycka? Och vari består den missgärning och synd som vi hava begått mot HERREN, vår Gud?",
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
då skall du svara dem: "Jo, edra fäder övergåvo mig, säger HERREN, och följde efter andra gudar och tjänade och tillbådo dem; ja, mig övergåvo de och höllo icke min lag.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
Och I själva haven gjort ännu mer ont, än edra fäder gjorde; ty se, I vandren var och en efter sitt onda hjärtas hårdhet, och I viljen icke höra mig.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Därför skall jag ock slunga eder bort ur detta land, till ett land son varken I eller edra fäder haven känt, och där Skolen I få tjäna andra gudar både dag och natt; ty jag skall icke hava någon misskund med eder."
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
Se, därför skola dagar komma, säger HERREN, då man icke mer skall säga: "Så sant HERREN lever, han som har fört Israels barn upp ur Egyptens land",
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
utan: "Så sant HERREN lever, han som har fört Israels barn upp ur nordlandet, och ur alla andra länder till vilka han hade drivit dem bort." Ty jag skall föra dem tillbaka till deras land, det som jag gav åt deras fäder.
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
Se, jag skall sända bud efter många fiskare, säger HERREN, och de skola fiska upp dem; och sedan skall jag sända bud efter många jägare, och de skola jaga dem ned från alla berg och alla höjder och ut ur stenklyftorna.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Ty mina ögon äro riktade på alla deras vägar; de kunna icke gömma sig för mitt ansikte och deras missgärning är icke fördold för mina ögon.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Och först skall jag i dubbelt mått vedergälla dem för deras missgärning och synd, för att de hava oskärat mitt land, i det att de hava uppfyllt min arvedel med sina styggeliga och skändliga avgudars döda kroppar.
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
HERRE, du min starkhet och mitt värn, du min tillflykt på nödens dag, till dig skola hedningarna komma från jordens ändar och skola säga: "Allenast lögn hava våra fäder fått i arv. fåfängliga avgudar, av vilka ingen kan hjälpa.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Kan väl en människa göra sig gudar? Nej, de gudarna äro inga gudar.
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
Därför vill jag nu denna gång låta dem förnimma det, jag vill låta dem känna min hand och min makt, för att de må veta att mitt namn är HERREN.

< Jeremiah 16 >