< Jeremiah 16 >
1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Кувынтул Домнулуй мь-а ворбит астфел:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
„Сэ ну-ць ей невастэ ши сэ н-ай ын локул ачеста нич фий, нич фийче!”
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Кэч аша ворбеште Домнул деспре фиий ши фийчеле каре се вор наште ын локул ачеста, деспре мамеле каре-й вор наште ши деспре таций лор каре ле вор да наштере ын цара ачаста:
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
„Вор мури доборыць де боалэ ря. Нимень ну-й ва плынӂе, нич ну-й ва ынгропа, чи вор фи ка ун гуной пе пэмынт; вор пери де сабие ши де фоамете, ши трупуриле лор моарте вор служи ка хранэ пэсэрилор черулуй ши фярелор пэмынтулуй.”
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Кэч аша ворбеште Домнул: „Сэ ну интри ын ничо касэ де жале, сэ ну плынӂь ын еа ши нич сэ ну те бочешть ку ей, кэч Мь-ам луат ынапой де ла попорул ачеста пачя Мя”, зиче Домнул, „бунэтатя ши ындураря Мя.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Ши марь, ши мичь, тоць вор мури ын цара ачаста ши ну вор фи ынгропаць: нимень ну-й ва плынӂе, нимень ну-шь ва фаче тэетурь дин причина лор ши ну се ва раде пентру ей.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
Нимень ну ле ва пуне маса ын тимпул желирий ка сэ-й мынгые пентру чел морт ши нимень ну ле ва ынтинде пахарул мынгыерий пентру татэл сау пентру мама лор.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
Сэ ну интри нич ынтр-о касэ де петречере, ка сэ те ашезь ку ей, сэ мэнынчь ши сэ бей.”
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Кэч аша ворбеште Домнул оштирилор, Думнезеул луй Исраел: „Ятэ, вой фаче сэ ынчетезе ын локул ачеста, суб окий воштри ши ын зилеле воастре, стригэтеле де букурие ши стригэтеле де веселие, кынтечеле мирелуй ши кынтечеле миресей.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
Кынд вей вести попорулуй ачестуя тоате ачесте лукрурь, ей ыць вор зиче: ‘Пентру че не аменинцэ Домнул ку тоате ачесте марь ненорочирь? Че нелеӂюире ши че пэкат ам фэкут ымпотрива Домнулуй Думнезеулуй ностру?’
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Атунч сэ ле рэспунзь: ‘Пэринций воштри М-ау пэрэсит’, зиче Домнул, ‘с-ау дус дупэ алць думнезей, ле-ау служит ши с-ау ынкинат ынаинтя лор, яр пе Мине М-ау пэрэсит ши н-ау пэзит Леӂя Мя!
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
Ши вой аць фэкут ши май рэу декыт пэринций воштри, кэч ятэ кэ фиекаре умблаць дупэ порнириле инимий воастре реле ши ну М-аскултаць.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Де ачея, вэ вой мута дин цара ачаста ынтр-о царэ пе каре н-аць куноскут-о нич вой, нич пэринций воштри ши аколо вець служи алтор думнезей, зи ши ноапте, кэч ну вэ вой ерта!’
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
Де ачея, ятэ, вин зиле”, зиче Домнул, „кынд ну се ва май зиче: ‘Виу есте Домнул, каре а скос дин цара Еӂиптулуй пе копиий луй Исраел!’
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
Чи се ва зиче: ‘Виу есте Домнул, каре а скос пе копиий луй Исраел дин цара де ла мязэноапте ши дин тоате цэриле унде-й изгонисе!’ Кэч ый вой адуче ынапой ын цара лор, пе каре о дэдусем пэринцилор лор.
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
Ятэ, тримит о мулциме де пескарь”, зиче Домнул, „ши-й вор пескуи; ши, дупэ ачея, вой тримите о мулциме де вынэторь ши-й вор вына пе тоць мунций ши пе тоате дялуриле ши ын крэпэтуриле стынчилор.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Кэч окий Мей сунт ку луаре аминте ла тоате кэиле лор; еле ну сунт аскунсе ынаинтя Фецей Меле ши нелеӂюиря лор ну есте аскунсэ де привириле Меле.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Де ачея ле вой рэсплэти май ынтый ындоит нелеӂюиря ши пэкатул лор, пентру кэ Мь-ау спуркат цара, пентру кэ Мь-ау умплут моштениря ку трупуриле моарте але жертфелор адусе идолилор лор ши ку урычуниле лор.”
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
Доамне, тэрия, четэцуя ши скэпаря мя ын зиуа неказулуй! Нямуриле вор вени ла Тине де ла марӂиниле пэмынтулуй ши вор зиче: „Пэринций ноштри н-ау моштенит декыт минчунэ, идоль дешерць, каре ну сунт де ничун ажутор!”
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Кум поате омул сэ-шь факэ думнезей каре ну сунт думнезей?
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
„Де ачея ятэ кэ ле арэт де дата ачаста ши-й фак сэ штие путеря ши тэрия Мя, ши вор куноаште кэ Нумеле Меу есте Домнул.