< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
بار دیگر خداوند با من سخن گفت و فرمود:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
«تو نباید در چنین مکانی ازدواج کنی و صاحب فرزند شوی،
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
چون کودکانی که در اینجا به دنیا بیایند همراه پدران و مادرانشان
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
در اثر بیماریهای کشنده خواهند مرد؛ کسی برای آنها ماتم نخواهد گرفت؛ جنازه‌هایشان دفن نخواهند شد بلکه همچون فضله بر روی زمین باقی خواهند ماند. آنها در اثر جنگ و قحطی کشته خواهند شد و لاشه‌هایشان را لاشخورها و جانوران خواهند خورد.
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
من برکت خود را از ایشان گرفته‌ام و از احسان و رحمت خود محرومشان کرده‌ام؛ پس تو برای آنها نه ماتم بگیر و نه گریه کن!
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
در این سرزمین چه ثروتمند و چه فقیر، همه خواهند مرد، ولی جنازه‌هایشان دفن نخواهند شد؛ نه کسی برای آنها ماتم خواهد گرفت، نه خود را برای ایشان مجروح خواهد کرد و نه موهای سرش را خواهد تراشید،
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
و نه کسی برای تسلی‌شان با آنها بر سر سفره خواهد نشست؛ حتی در مرگ والدینشان نیز هیچ‌کس با ایشان همدردی نخواهد کرد!
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
«پس تو از هم اکنون دیگر در مهمانیها و جشنهای آنها شرکت نکن، و حتی با ایشان غذا هم نخور!
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
چون من، خداوند لشکرهای آسمان، خدای بنی‌اسرائیل در طول زندگی‌تان و در برابر چشمانتان، به تمام خنده‌ها و خوشیها، به همۀ نغمه‌های شاد، و همهٔ جشنهای عروسی پایان خواهم داد.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
«وقتی تمام این چیزها را به مردم بازگو کنی، خواهند پرسید:”چرا خداوند چنین مجازات سختی برای ما در نظر گرفته است؟ مگر تقصیرمان چیست؟ به یهوه خدای‌مان چه گناهی کرده‌ایم؟“
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
آنگاه به ایشان بگو که خداوند چنین پاسخ می‌دهد:”علّت این است که پدران شما مرا ترک کرده، از بتها پیروی نمودند و قوانین مرا اطاعت نکردند.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
ولی شما از پدرانتان هم بدکارتر هستید. شما در پی هوسهای گناه‌آلود خود می‌روید و نمی‌خواهید مرا پیروی کنید؛
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
از این رو شما را از این سرزمین بیرون انداخته، به سرزمینی خواهم راند که هرگز نه خود شما آنجا بوده‌اید و نه اجدادتان؛ در آنجا می‌توانید شبانه روز به بت‌پرستی بپردازید و من هم دیگر بر شما رحم نخواهم نمود.“»
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
با این حال خداوند می‌فرماید: «زمانی می‌آید که مردم هرگاه بخواهند در مورد کارهای شگفت‌انگیز من گفتگو کنند، دیگر اعمال عجیب مرا به هنگام بیرون آوردن بنی‌اسرائیل از مصر، ذکر نخواهند نمود، بلکه در این باره سخن خواهند گفت که من چگونه بنی‌اسرائیل را از سرزمین شمال و همۀ سرزمینهایی که ایشان را به آنها رانده بودم، باز آورده‌ام. بله، من ایشان را به سرزمینی که به پدرانشان داده‌ام باز خواهم گرداند!»
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
خداوند می‌فرماید: «اکنون به دنبال ماهیگیران بسیار می‌فرستم تا بیایند و شما را از اعماق دریا که در آنجا از ترس خشم من خود را پنهان کرده‌اید، صید کنند! همچنین به دنبال شکارچیان بسیار خواهم فرستاد تا شما را شکار کنند، همان‌گونه که گوزن را در کوهها و تپه‌ها، و بز کوهی را در میان صخره‌ها شکار می‌کنند.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
من با دقت مراقب رفتار شما هستم و هیچ عمل شما از نظر من مخفی نیست؛ هرگز نمی‌توانید گناهانتان را از من پنهان کنید؛
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
من به سبب همهٔ آنها شما را دو برابر مجازات می‌کنم، چون با بتهای نفرت‌انگیز خود، زمین مرا آلوده کرده‌اید و آن را با اعمال بدتان پر ساخته‌اید.»
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
ای خداوند، ای قوت من، ای پشتیبان من، که به هنگام سختی پناهگاهم هستی، قومها از سراسر جهان نزد تو آمده، خواهند گفت: «پدران ما چقدر نادان بودند که خدایان پوچ و دروغین را پیروی می‌کردند!
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
آیا انسان می‌تواند برای خود خدا بسازد؟ بُتی که به دست انسان ساخته شود خدا نیست!»
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
خداوند می‌گوید: «قدرت و توانایی خود را به آنها نشان خواهم داد و سرانجام به ایشان خواهم فهماند که تنها من خداوند هستم.»

< Jeremiah 16 >