< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
«برای خود زنی مگیر و تو را در این مکان پسران و دختران نباشد.۲
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
زیرا خداونددرباره پسران و دخترانی که در این مکان مولودشوند و درباره مادرانی که ایشان را بزایند وپدرانی که ایشان را در این زمین تولید نمایند چنین می‌گوید:۳
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
به بیماریهای مهلک خواهند مرد. برای ایشان ماتم نخواهند گرفت و دفن نخواهندشد بلکه بر روی زمین سرگین خواهند بود. و به شمشیر و قحط تباه خواهند شد و لاشهای ایشان غذای مرغان هوا و وحوش زمین خواهد بود.۴
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
زیرا خداوند چنین می‌گوید: به خانه نوحه گری داخل مشو و برای ماتم گرفتن نرو و برای ایشان تعزیت منما زیرا خداوند می‌گوید که سلامتی خود یعنی احسان و مراحم خویش را از این قوم خواهم برداشت.۵
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
هم بزرگ و هم کوچک در این زمین خواهند مرد و دفن نخواهند شد. و برای ایشان ماتم نخواهند گرفت و خویشتن را مجروح نخواهند ساخت و موی خود را نخواهند تراشید.۶
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
و برای ماتم گری نان را پاره نخواهند کرد تاایشان را برای مردگان تعزیت نمایند و کاسه تعزیت را با ایشان برای پدر یا مادر ایشان هم نخواهند نوشید.۷
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
و تو به خانه بزم داخل مشو و باایشان برای اکل و شرب منشین.۸
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
زیرا که یهوه صبایوت خدای اسرائیل چنین می‌گوید: اینک من در ایام شما و در نظر شما آواز خوشی و آوازشادمانی و آواز داماد و آواز عروس را از این مکان خواهم برداشت.۹
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
و هنگامی که همه این سخنان را به این قوم بیان کنی و ایشان از توبپرسند که خداوند از چه سبب تمامی این بلای عظیم را به ضد ما گفته است و عصیان و گناهی که به یهوه خدای خود ورزیده‌ایم چیست؟۱۰
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
آنگاه تو به ایشان بگو: خداوند می‌گوید: از این جهت که پدران شما مرا ترک کردند و خدایان غیر را پیروی نموده، آنها راعبادت و سجده نمودند و مرا ترک کرده، شریعت مرا نگاه نداشتند.۱۱
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
و شما ازپدران خویش زیاده شرارت ورزیدید چونکه هریک از شما سرکشی دل شریر خود را پیروی نمودید و به من گوش نگرفتید.۱۲
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
بنابراین من شمارا از این زمین به زمینی که شما و پدران شماندانسته‌اید خواهم‌انداخت و در آنجا شبانه‌روزخدایان غیر را عبادت خواهید نمود زیرا که من برشما ترحم نخواهم نمود.۱۳
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
«بنابراین خداوند می‌گوید: اینک ایامی می‌آید که بار دیگر گفته نخواهد شد قسم به حیات یهوه که بنی‌اسرائیل را از زمین مصر بیرون آورد.۱۴
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
بلکه قسم به حیات یهوه که بنی‌اسرائیل را از زمین شمال و همه زمینهایی که ایشان را به آنها رانده بود برآورد. زیرا من ایشان را به زمینی که به پدران ایشان داده‌ام باز خواهم آورد.۱۵
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
خداوند می‌گوید: اینک ماهی گیران بسیار راخواهم فرستاد تا ایشان را صید نمایند و بعد از آن صیادان بسیار را خواهم فرستاد تا ایشان را از هرکوه و هر تل و از سوراخهای صخره‌ها شکارکنند.۱۶
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
زیرا چشمانم بر همه راههای ایشان است و آنها از نظر من پنهان نیست و عصیان ایشان از چشمان من مخفی نی.۱۷
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
و من اول عصیان وگناهان ایشان را مکافات مضاعف خواهم رسانیدچونکه زمین مرا به لاشهای رجاسات خود ملوث نموده و میراث مرا به مکروهات خویش مملوساخته‌اند.»۱۸
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
‌ای خداوند که قوت من و قلعه من و در روزتنگی پناهگاه من هستی! امت‌ها از کرانهای زمین نزد تو آمده، خواهند گفت: پدران ما جز دروغ واباطیل و چیزهایی را که فایده نداشت وارث هیچ نشدند.۱۹
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
آیا می‌شود که انسان برای خودخدایان بسازد و حال آنکه آنها خدا نیستند؟۲۰
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
«بنابراین هان این مرتبه ایشان را عارف خواهم گردانید بلی دست خود و جبروت خویش را معروف ایشان خواهم ساخت وخواهند دانست که اسم من یهوه است.»۲۱

< Jeremiah 16 >