< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
TUHAN berbicara lagi kepadaku, kata-Nya,
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
"Jangan kawin dan mendapat anak di tempat ini.
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Akan Kukatakan kepadamu apa yang akan terjadi dengan anak-anak yang lahir di sini dan dengan orang tuanya.
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
Mereka akan mati diserang penyakit yang membawa maut, dan mereka akan tewas dalam pertempuran atau mati kelaparan. Tak seorang pun akan menangisi atau menguburkan mereka. Mayat mereka akan terserak seperti pupuk di tanah, dan dimakan burung serta binatang buas.
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Janganlah pergi ke rumah orang yang sedang berduka, Yeremia. Jangan berkabung untuk siapa pun. Aku tidak akan memberkati umat-Ku lagi dengan kesejahteraan, dan tidak juga akan menunjukkan rasa sayang atau belas kasihan kepada mereka.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Orang kaya dan orang miskin di negeri ini akan mati tanpa ada yang menguburkan mereka. Tak seorang pun akan menyiksa diri atau menggunduli kepalanya sebagai tanda berkabung untuk mereka.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
Tak ada pula yang mau mengadakan selamatan untuk menghibur orang yang sedang berkabung. Tidak ada yang ikut berduka cita bahkan dengan orang yang kehilangan ayah atau ibunya.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
Jangan masuk ke rumah orang yang sedang berpesta. Jangan makan minum dengan mereka.
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Dengarkan apa yang Aku, TUHAN Yang Mahakuasa, Allah Israel, hendak katakan kepadamu. Suara gembira dan sukacita serta keramaian pesta kawin akan Kuhentikan semua. Hal itu akan disaksikan oleh orang-orang yang hidup di zamanmu ini.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
Apabila engkau menyampaikan semua ini kepada mereka, barangkali mereka akan bertanya mengapa Aku mau menghukum mereka begitu keras. Mereka akan bertanya apa kesalahan dan dosa mereka terhadap Aku, TUHAN Allah mereka.
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Beritahukanlah kepada mereka bahwa Aku berkata begini, 'Leluhurmu telah meninggalkan Aku untuk menyembah dan beribadat kepada ilah-ilah lain. Mereka mengabaikan Aku dan tidak mau taat kepada peraturan-peraturan-Ku.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
Tapi kamu melakukan yang lebih jahat lagi. Kamu keras kepala dan hanya mengikuti kemauanmu sendiri yang jahat. Kamu tidak mau taat kepada-Ku.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Karena itu, kamu akan Kuusir dari negeri ini dan Kubuang ke sebuah negeri yang sama sekali asing bagimu dan bagi leluhurmu. Di sana kamu akan beribadat siang malam kepada ilah-ilah lain, dan Aku tidak akan berbelaskasihan kepadamu.'"
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
TUHAN berkata, "Akan datang waktunya orang tidak lagi bersumpah demi Aku, Allah yang hidup, yang membawa umat Israel keluar dari Mesir,
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
melainkan demi Aku, Allah yang hidup, yang membawa umat Israel keluar dari sebuah negeri di utara dan dari semua negeri lain di mana mereka telah Kuceraiberaikan. Mereka akan Kubawa kembali ke tanah air mereka, negeri yang telah Kuberikan kepada leluhur mereka."
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
TUHAN berkata, "Aku hendak memanggil banyak nelayan untuk menangkap orang-orang ini. Kemudian Aku akan memanggil banyak pemburu untuk memburu mereka di setiap gunung dan bukit, dan di gua-gua bukit batu.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Aku melihat segala yang mereka lakukan. Tak ada yang tersembunyi bagi-Ku; dosa-dosa mereka pun sudah Kulihat.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Dosa dan kejahatan mereka akan Kubalas dengan hukuman dua kali lipat, karena mereka sudah menajiskan negeri-Ku dengan banyak berhala. Berhala-berhala itu tak bernyawa seperti mayat."
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
TUHAN, Engkaulah yang melindungi aku dan memberikan kekuatan kepadaku; Engkau menolong aku pada masa kesukaran. Bangsa-bangsa dari ujung bumi akan datang kepada-Mu dan berkata, "Leluhur kami hanya mempunyai ilah palsu yang sama sekali tak berguna.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Dapatkah manusia membuat ilahnya sendiri? Tentu tidak! Yang dibuatnya itu pasti bukan Allah."
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
"Karena itu," kata TUHAN, "sekali ini Aku akan membuat bangsa-bangsa merasakan kekuasaan dan kekuatan-Ku supaya untuk selama-lamanya mereka akan tahu bahwa Akulah TUHAN."

< Jeremiah 16 >