< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Hĩndĩ ĩyo ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyanginyĩrire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
“Ndũkanahikanie ũgĩe na aanake kana airĩtu kũndũ gũkũ.”
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Nĩgũkorwo ũũ nĩguo Jehova ekuuga ũndũ ũkoniĩ aanake na airĩtu arĩa maciarĩirwo bũrũri ũyũ na ũkoniĩ atumia arĩa marĩ manyina mao na arũme arĩa marĩ maithe mao, atĩrĩ:
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
“Nĩmagakua gĩkuũ kiumanĩte na mĩrimũ mĩũru. Matigaacakaĩrwo kana mathikwo, no magaatuĩka ta rũrua rũharaganĩtio gũkũ thĩ. Makaaniinwo na rũhiũ rwa njora na ngʼaragu, nacio ciimba ciao igatuĩka, irio cia nyoni cia rĩera-inĩ na nyamũ cia gĩthaka.”
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Nĩgũkorwo Jehova ekuuga atĩrĩ: “Ndũkanatoonye mũciĩ ũrĩ na ndĩa ya mathiko; ndũgathiĩ gũcakaya kana gũcaayanĩra, nĩ ũndũ nĩnjeheretie kĩrathimo gĩakwa, na wendo wakwa, o na tha ciakwa harĩ andũ aya,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
“Andũ othe, anene na arĩa anini, nĩmagakuĩra bũrũri-inĩ ũyũ. Matigaathikwo kana macakaĩrwo, na gũtirĩ mũndũ ũgetiihangia kana enjwo mũtwe nĩ ũndũ wao.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
Gũtirĩ mũndũ ũkaaheana irio cia kũhooreria acio maracakaĩra arĩa makuĩte, o na akorwo nĩ ithe kana nyina, o na gũtirĩ mũndũ ũkaaheana kĩndũ gĩa kũnyua nĩguo amagirie maithori.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
“Ningĩ ndũkanatoonye mũciĩ ũrĩ na gĩathĩ, atĩ nĩguo ũikare thĩ nao mũrĩe na mũnyue.
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Nĩgũkorwo Jehova, Mwene-Hinya-Wothe, o we Ngai wa Isiraeli, ekuuga atĩrĩ: ‘Matukũ-inĩ manyu nĩmũkeonera na maitho manyu ngakinyia mĩgambo ya ndũrũhĩ na ya gĩkeno mũthia o na niine mĩgambo ya mũhiki na mũhikania kũndũ gũkũ.’
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
“Rĩrĩa ũkeera andũ aya maũndũ macio mothe nao makũũrie atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte Jehova atũtuĩre mwanangĩko mũnene ũguo? Kaĩ twĩkĩte ihĩtia rĩrĩkũ? Nĩ mehia marĩkũ twĩhĩirie Jehova Ngai witũ?’
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Hĩndĩ ĩyo ũmeere atĩrĩ: Jehova ekuuga atĩrĩ, ‘Nĩ tondũ maithe manyu nĩmandirikire, makĩrũmĩrĩra ngai ingĩ, magĩcitungatagĩra na magĩcihooyaga. Nĩmandirikire na makĩaga kũrũmia watho wakwa.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
No inyuĩ nĩmwĩkĩte maũndũ ma waganu mũgakĩra maithe manyu. Ta rorai muone ũrĩa o ũmwe wanyu arũmĩrĩire ũremi wa ngoro yake thũku, handũ ha kũnjathĩkĩra.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Nĩ ũndũ ũcio nĩngũmũrutũrũra muume bũrũri ũyũ mũthiĩ bũrũri mũtooĩ inyuĩ ene, o na kana ũkamenywo nĩ maithe manyu, na mũrĩ kũu nĩmũgatungatagĩra ngai ingĩ mũthenya na ũtukũ, nĩgũkorwo ndigũcooka kũmwĩka maũndũ mega.’”
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
Jehova ekuuga atĩrĩ, “O na kũrĩ ũguo, matukũ nĩmarooka rĩrĩa andũ matagacooka kuuga atĩrĩ, ‘Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo, ũrĩa warutire andũ a Isiraeli kuuma bũrũri wa Misiri,’
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
no makoigaga atĩrĩ, ‘Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo, ũrĩa warutire andũ a Isiraeli bũrũri ũrĩa ũrĩ mwena wa gathigathini, na akĩmaruta mabũrũri-inĩ mothe kũrĩa aamathaamĩirie.’ Nĩgũkorwo nĩngamacookia bũrũri-inĩ ũrĩa ndaaheire maithe mao.”
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
Jehova ekuuga atĩrĩ, “No rĩrĩ, nĩngũtũmana gwĩtwo ategi a thamaki aingĩ, nao nĩmakamatega. Thuutha wa ũguo njooke ndũmanĩre aguĩmi aingĩ, nao nĩmakamaguĩma irĩma-inĩ, na tũrĩma-inĩ tuothe, na mĩatũka-inĩ ya ndwaro cia mahiga.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Maitho makwa nĩmoonaga mĩthiĩre yao yothe; ndĩngĩhithĩka harĩ niĩ, o namo mehia mao matingĩhithwo atĩ nĩguo maitho makwa mage kũmona.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Ngaamarĩhia maita meerĩ nĩ ũndũ wa waganu wao na mehia mao, nĩ ũndũ nĩmathaahĩtie bũrũri wakwa na mĩhaano ĩtarĩ muoyo mĩmeneku mũno, na makaiyũria igai rĩakwa na mĩhianano ĩrĩ magigi.”
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
Atĩrĩrĩ Wee Jehova, o wee hinya wakwa, na kĩirigo gĩakwa kĩrũmu, o wee rĩũrĩro rĩakwa hĩndĩ ya mathĩĩna, ndũrĩrĩ igooka harĩwe ciumĩte ituri-inĩ cia thĩ, ciuge atĩrĩ, “Maithe maitũ matiarĩ na kĩndũ tiga ngai cia maheeni, o mĩhianano ĩyo ĩtarĩ kĩene na ĩtarĩ ũndũ mwega yamekĩire.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Andũ nĩmethondekagĩra ngai ciao ene? Ĩĩ, no rĩrĩ, icio ti ngai!”
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
“Tondũ ũcio nĩngamaruta maamenye, ihinda-inĩ rĩĩrĩ nĩguo ngaamaruta ũhoro wa ũhoti na hinya wakwa. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ rĩĩtwa rĩakwa nĩ Jehova.

< Jeremiah 16 >