< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Et la parole de Yahvé me fut adressée, en disant:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
« Tu ne prendras pas de femme, et tu n'auras ni fils ni filles, dans ce lieu. »
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Car l'Éternel dit, au sujet des fils et des filles qui naîtront dans ce lieu, au sujet de leurs mères qui les auront enfantés, et au sujet de leurs pères qui les auront engendrés dans ce pays:
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
« Ils mourront d'une mort douloureuse. On ne les pleurera pas, on ne les enterrera pas. Ils seront comme du fumier à la surface de la terre. Ils seront consumés par l'épée et par la famine. Leurs cadavres serviront de nourriture aux oiseaux du ciel et aux animaux de la terre. »
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Car Yahvé dit: « N'entre pas dans la maison de deuil. N'allez pas vous lamenter. Ne les pleurez pas, car j'ai retiré à ce peuple ma paix, dit l'Éternel, ma bonté et ma miséricorde.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Les grands et les petits mourront dans ce pays. On ne les enterrera pas. On ne se lamentera pas sur eux, on ne se coupera pas, on ne se rendra pas chauve pour eux.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
On ne rompra pas le pain pour eux dans le deuil, pour les consoler de leur mort. On ne leur donnera pas la coupe de consolation à boire pour leur père ou pour leur mère.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
« Tu n'entreras pas dans la maison du festin pour t'asseoir avec eux, pour manger et pour boire. »
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Car l'Éternel des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Voici, je vais faire cesser de ce lieu, sous vos yeux et de votre temps, la voix de la joie et la voix de l'allégresse, la voix du fiancé et la voix de la fiancée.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
Lorsque tu diras toutes ces choses à ce peuple et qu'il te demandera: « Pourquoi Yahvé a-t-il prononcé contre nous tout ce malheur? », « Quelle est notre faute? », « Quel est le péché que nous avons commis contre Yahvé notre Dieu? »
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Tu leur diras: « Parce que vos pères m'ont abandonné, dit Yahvé, et qu'ils sont allés après d'autres dieux, qu'ils les ont servis, qu'ils se sont prosternés devant eux, qu'ils m'ont abandonné et qu'ils n'ont pas observé ma loi.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
Vous avez fait le mal plus que vos pères, car voici, vous marchez chacun selon l'obstination de son mauvais cœur, de sorte que vous ne m'écoutez pas.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
C'est pourquoi je vous chasserai de ce pays pour vous rendre dans le pays que vous n'avez pas connu, ni vous ni vos pères. Là, vous servirez d'autres dieux jour et nuit, car je ne vous ferai pas de cadeaux.
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
C'est pourquoi voici, les jours viennent, dit l'Éternel, où l'on ne dira plus: « L'Éternel est vivant, lui qui a fait monter les enfants d'Israël du pays d'Égypte »,
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
mais: « L'Éternel est vivant, lui qui a fait monter les enfants d'Israël du pays du nord et de tous les pays où il les avait chassés ». Je les ramènerai dans le pays que j'ai donné à leurs pères.
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
« Voici, j'enverrai de nombreux pêcheurs, dit Yahvé, et ils les pêcheront. Ensuite, j'enverrai beaucoup de chasseurs, et ils les chasseront de toutes les montagnes, de toutes les collines, et des fentes des rochers.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Car mes yeux sont sur toutes leurs voies. Ils ne sont pas cachés de ma face. Leur iniquité n'est pas cachée à mes yeux.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
D'abord je rétribuerai leur iniquité et leur péché au double, parce qu'ils ont souillé mon pays avec les cadavres de leurs choses détestables, et qu'ils ont rempli mon héritage de leurs abominations. »
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
Yahvé, ma force, ma forteresse, et mon refuge au jour de l'affliction, les nations viendront à toi des extrémités de la terre, et dira, « Nos pères n'ont hérité que de mensonges, la vanité et les choses dans lesquelles il n'y a aucun profit.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
L'homme doit-il se faire des dieux qui ne sont pas encore des dieux? »
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
« C'est pourquoi voici, je vais leur faire connaître, cette fois, je leur ferai connaître ma main et ma puissance. Alors ils sauront que mon nom est Yahvé ».

< Jeremiah 16 >