< Jeremiah 16 >

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
Ei sinun pidä ottaman itselles vaimoa, eikä siittämän poikia eli tyttäriä tässä paikassa.
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Sillä näin sanoo Herra niistä pojista ja tyttäristä, jotka tässä paikassa syntyvät, ja äideistä, jotka heitä synnyttävät, ja heidän isistänsä, jotka heitä tässä maassa siittävät:
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
Heidän pitää kuoleman sairaudessansa, ja ei heitä pidä itkettämän eli haudattaman, vaan heidän pitää loaksi kedolle tuleman; ja heidän pitää vielä sitte miekalla ja nälällä hukkuman, ja heidän ruumiinsa pitää linnuille taivaan alla ja eläimille maassa ruaksi tuleman.
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Sillä näin sanoo Herra: ei sinun pidä menemän murhehuoneesen, eikä menemän itkemään eli surkuttelemaan heitä; sillä minä olen ottanut pois minun rauhani tältä kansalta, sanoo Herra, ja minun armoni ja laupiuteni;
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Että sekä suuret että pienet pitää tässä maassa kuoleman, ja ei haudatuksi tuleman, ja ei yhdenkään pidä itkemän eli repimän itsiänsä, eikä ajeleman hiuksiansa heidän tähtensä.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
Ja ei myös pidä (leipää) jaettaman murheessa, että heitä lohdutettaisiin kuolleen tähden, eikä pidä annettaman juoda lohdutusmaljasta isänsä tähden ja äitinsä tähden.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
Ja ei pidä sinun menemän pitohuoneesen, istumaan heidän viereensä, syömään ja juomaan.
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Sillä näin sanoo Herra Zebaot, Israelin Jumala: katso, minä tahdon ottaa pois tästä siasta, teidän silmäinne edestä ja teidän eläissänne, ilon ja riemun äänen, yljän äänen ja morsiamen äänen.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
Ja kuin sinä nämät kaikki tälle kansalle sanonut olet, ja he sanovat sinulle: miksi Herra uhkaa meille kaikkea tätä suurta onnettomuutta? ja mikä on meidän pahatekomme ja syntimme, jolla me olemme rikkoneet Herraa, meidän Jumalaamme, vastaan?
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Niin sinun pitää sanoman heille: että teidän isänne, sanoo Herra, ovat hyljänneet minun, ja seuranneet muita jumalia, palvelleet niitä ja kumartaneet niitä; mutta minun ovat he hyljänneet, ja ei pitäneet minun lakiani.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
Ja te teette vielä pahemmin kuin teidän isänne; sillä katso, kukin elää oman pahan sydämensä sisun jälkeen, eikä yksikään tottele minua.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Sentähden minä tahdon ajaa teidät pois tästä maasta siihen maahan, josta ette te eikä teidän isänne mitään tiedä, siellä saatte te palvella muita jumalia yli päivää ja yötä, ja en minä tahdo siellä armoa näyttää teille.
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
Sentähden katso, se aika tulee, sanoo Herra, ettei sitte pidä enään sanottaman: niin totta kuin Herra elää, joka Israelin lapset Egyptin maalta on johdattanut,
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
Vaan, niin totta kuin Herra elää, joka Israelin lapset on johdattanut pohjan maasta ja kaikista maista, joihin hän heitä ajanut oli; sillä minä tahdon antaa heidän tulla jälleen heidän maahansa, jonka minä heidän isillensä antanut olen.
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
Katso, minä lähetän monta kalamiestä, sanoo Herra, heitä onkimaan; ja sitte lähetän minä monta metsämiestä, heitä käsittämään kaikilla vuorilla, kaikilla kukkuloilla ja kaikissa kiviraunioissa.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Sillä minun silmäni näkee kaikki heidän tiensä, ja ei ne ole peitetyt minun edessäni; ja heidän pahatekonsa on minun silmäini edessä salaamatoin.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Ensisti pitää minun kaksinkertaisesti maksaman heidän pahat tekonsa ja syntinsä, että he ovat saastuttaneet minun maani kauhistustensa raadoilla, ja kauhistuksellansa täyttivät he minun perintöni.
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
Herra, sinä olet väkevyyteni ja voimani, ja turvani hädässä; pakanat tulevat sinun tykös maailman ääristä ja sanovat: meidän isämme ovat tosin pitäneet vääriä ja turhia jumalia, jotka ei mitään auttaa taida.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Kuinka taitaa ihminen tehdä hänellensä jumalia, jotka ei kuitenkaan jumalia olekaan?
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
Sentähden katso, minä tahdon opettaa heitä tällä haavalla, ja tehdä heille minun käteni ja valtani tiettäväksi; ja heidän pitää ymmärtämän, että minun nimeni on Herra.

< Jeremiah 16 >