< Jeremiah 16 >
1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Eka wach Jehova Nyasaye nobirona:
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
“Kik ikendi mondo kik inywol yawuowi kata nyiri ka.”
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
Nimar ma e gima Jehova Nyasaye wacho kuom yawuowi gi nyiri monywol e pinyni kendo kuom mon ma minegi kod chwo ma wuonegi:
4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
“Ginitho gi tuoche maricho richo. Ok nogo nduchgi kata ik bende ok noikgi, to ginichal ka owuoyo manie lowo. Ligangla kod kech noneg-gi, to ringregi nobed chiemb winy mafuyo e kor polo kod le manie piny.”
5 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
Nimar ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Kik idonj e ot mantiere chiemb liel; kik iywagi bende kik ikechgi, nikech asegolo gwethna, herana kod ngʼwonona kuom jogi.
6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
Joma iwuoro to gi ji ajiya notho e pinyni. Ok noikgi kendo ok noywag-gi, bende onge ngʼama nongʼad dende kata lielo wiye nikech gin.
7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
Onge ngʼama nochiw chiemo mondo oogo joma goyo nduch joma otho kata mana newuoro kata miyo bende onge ngʼama nomigi math mondo oogi.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
“Kendo kik idonj e ot mantiere nyasi ma ibed piny mondo ichiem kendo metho.
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
Nimar ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho: E ndalo ngimau kendo ka uneno anatiek koko mar ilo kae kod wende mag nyako midhi kendi kod wuowi madhi kendo.
10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
“Ka inyiso jogi gigi duto to gipenji ni, ‘Angʼo momiyo Jehova Nyasaye osechikonwa masira malich ka ma? Angʼo ma wasetimo marach? Richo mane ma wasetimo ne Jehova Nyasaye ma Nyasachwa?’
11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
Eka iwachnegi ni Jehova Nyasaye owacho ni, ‘Nikech wuoneu nojwangʼa, mi giluwo bangʼ nyiseche manono mi gitiyonegi kendo lamogi. Ne gikweda kendo ok girito chikna.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
To usebedo joma timbegi mono moloyo wuoneu. Ne kaka ngʼato ka ngʼato kuomu luwo timbe manono mag chuny kar mondo gilwora.
13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
Kuom mano, anawitu oko mar pinyni nyaka e piny ma un kata wuoneu ok osengʼeyo, kendo kanyo unutine nyiseche moko manono odiechiengʼ gi otieno, nimar ok anangʼwon-nu.’”
14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
Jehova Nyasaye owacho niya, “Kata kamano, ndalo biro, ma dhano ok nochak owachi ni, ‘Akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima, manogolo jo-Israel Misri,’
15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
to giniwach ni, ‘Akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima, manogolo jo-Israel e piny ma yo nyandwat kendo koa e pinje duto kama ne oseriembogie.’ Nimar anadwog-gi e piny mane amiyo kweregi.”
16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
Jehova Nyasaye owacho niya, “To anaor jolupo mangʼeny kendo ginimakgi. Bangʼ mano anaor jodwar mangʼeny, kendo ginidwargi e got maduongʼ kod mago matindo kendo e kuonde pondo mokunyore e lwendni.
17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
Wengena ne oneno timbegi duto; ok gipondona, bende richogo ok opondona.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
Anachulgi nyadiriyo kuom timbegi mamono kod richo mag-gi, nikech gisenjawo pinya kod gigi mopa maonge ngima kendo gisepongʼo girkeni mara gi nyisechegi manono maonge tich.”
19 Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
Yaye Jehova Nyasaye, in e tekona kod ohingana, kar pondona e ndalo chandruok, in ema ogendini nobi iri koa e tungʼ piny ka tungʼ piny mi giwachi ni, “Wuonewa ne onge gimoro to mana nyiseche manono mag miriambo, nyiseche mopa maonge tich mane ok otimonegi ber moro amora.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
Bende ji loso nyisechegi giwegi? Ee, to ok gin nyiseche!”
21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.
“Emomiyo anapuonjgi kendo tinendeni anapuonjgi, tekona gi nyalona. Eka giningʼe ni nyinga en Jehova Nyasaye.”