< Jeremiah 15 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
Men HERREN sade till mig; Om än Mose och Samuel trädde inför mig, så skulle min själ dock icke vända sig till detta folk. Driv dem bort ifrån mitt ansikte och låt dem gå.
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
Och om de fråga dig: "Vart skola vi gå?", så skall du svara dem: Så säger HERREN: I pestens våld den som hör pesten till, i svärdets våld den som hör svärdet till, i hungerns våld den som hör hungern till, i fångenskapens våld den som hör fångenskapen till.
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
Fyra slags hemsökelser skall jag låta komma över dem, säger HERREN: svärdet, som skall dräpa dem, hundarna, som skola släpa bort dem, himmelens fåglar och vilddjuren på marken, som skola äta upp och fördärva dem.
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
Och jag skall göra dem till en varnagel för alla riken på jorden, till straff för det som Manasse, Hiskias son, Juda konung, har gjort i Jerusalem.
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
Ty vem kan hava misskund med dig, Jerusalem, och vem kan ömka dig, och vem kan vilja komma för att fråga om det står väl till med dig?
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
Du själv försköt mig, säger HERREN; du gick din väg bort. Därför uträckte jag mot dig min hand och fördärvade dig; jag hade tröttnat att förbarma mig.
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
Ja, jag kastade dem med kastskovel vid landets portar, jag gjorde föräldrarna barnlösa, jag förgjorde mitt folk, då de ej ville vända om från sina vägar.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
Deras änkor blevo genom mig talrikare än sanden i havet; över mödrarna till deras unga lät jag förhärjare komma mitt på ljusa dagen; plötsligt lät jag ångest och förskräckelse falla över dem.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
Om en moder än hade sju söner, måste hon dock giva upp andan i sorg; hennes sol gick ned, medan det ännu var dag, hon måste bliva till skam och blygd. Och vad som är kvar av dem skall jag giva till pris åt deras fienders svärd, säger HERREN
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
"Ve mig, min moder, att du har fött mig, mig som är till kiv och träta för hela landet! Jag har icke drivit ocker, ej heller har någon behövt ockra på mig; likväl förbanna de mig alla."
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
Men HERREN svarade: "Sannerligen, jag skall styrka dig och låta det gå dig väl. Sannerligen, jag skall så göra, att dina fiender komma och bönfalla inför dig i olyckans och nödens tid.
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
Kan man bryta sönder järn, järn från norden, eller koppar?" --
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
Ditt gods och dina skatter skall jag lämna till plundring, och det utan betalning, till straff för allt vad du har syndat i hela ditt land.
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
Och jag skall låta dina fiender föra dig in i ett land som du icke känner. Ty min vredes eld är upptänd; mot eder skall det brinna.
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
HERRE, du vet det. Tänk på mig och låt dig vårda om mig, och skaffa mig hämnd på mina förföljare; tag mig icke bort, du som är långmodig. Betänk huru jag bär smälek för din skull
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
När jag fick dina ord, blevo de min spis, ja, dina ord blevo för mig mitt hjärtas fröjd och glädje; ty jag är uppkallad efter ditt namn, HERRE, härskarornas Gud.
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
Jag har icke suttit i gycklares samkväm och förlustat mig där; för din hands skull har jag måst sitta ensam, ty du har uppfyllt mig med förgrymmelse.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
Varför skall jag då plågas så oavlåtligt, och varför är mitt sår så ohelbart? Det vill ju icke läkas. Ja, du bliver för mig såsom en försinande bäck, så som ett vatten som ingen kan lita på.
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
Därför säger HERREN så: Om du vänder åter, så vill jag låta dig komma åter och bliva min tjänare. Och om du frambär ädel metall utan slagg, så skall du få tjäna mig såsom mun. Dessa skola då vända åter till dig, men du skall icke vända åter till dem.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
Och jag skall göra dig inför detta folk till en fast kopparmur, så att de icke skola bliva dig övermäktiga, om de vilja strida mot dig; ty jag är med dig och vill frälsa dig och vill hjälpa dig, säger HERREN.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
Jag skall hjälpa dig ut ur de ondas våld och skall förlossa dig ur våldsverkarnas hand.

< Jeremiah 15 >