< Jeremiah 15 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
Wtedy PAN powiedział do mnie: Choćby Mojżesz i Samuel stanęli przede mną, nie miałbym serca do tego ludu. Wypędź ich sprzed mego oblicza i niech idą precz.
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
A jeśli zapytają: Dokąd pójdziemy? Wtedy im powiesz: Tak mówi PAN: Kto [przeznaczony] na śmierć, [pójdzie] na śmierć; kto pod miecz – pod miecz, kto na głód – na głód, a kto na niewolę – w niewolę.
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
I nawiedzę ich czterema rodzajami [kar], mówi PAN: Mieczem, aby zabijał, psami, aby rozszarpywały, ptactwem nieba i zwierzętami ziemi, aby pożerały i niszczyły.
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
I sprawię, że zostaną wysiedleni do wszystkich królestw ziemi z powodu Manassesa, syna Ezechiasza, króla Judy, za to, co uczynił w Jerozolimie.
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
Któż bowiem zlituje się nad tobą, Jerozolimo? Któż się użali nad tobą? Któż zboczy z drogi, aby zapytać, jak ci się powodzi?
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
Ty mnie opuściłaś, mówi PAN, odwróciłaś się [ode mnie]. Dlatego wyciągnę na ciebie moją rękę, aby cię wytracić; zmęczyłem się żałowaniem.
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
Rozwieję ich wiejadłem w bramach [tej] ziemi, osierocę [i] wygubię mój lud, [bo] nie zawrócili ze swoich dróg.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
Ich wdów więcej mi się namnożyło niż nadmorskich piasków. Sprowadziłem na nich, na matki młodzieńców, niszczyciela w południe. Sprawię, że nagle napadnie na to miasto, a [jego mieszkańcy] będą przestraszeni.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
Mdleje ta, która urodziła siedmioro, wyzionęła ducha; jeszcze za dnia zaszło jej słońce. Zapłonęła i zawstydziła się. A ich resztkę wydam na pastwę miecza przed ich wrogami, mówi PAN.
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
Biada mi, moja matko, że urodziłaś mnie, mężczyznę kłótni i sporu na całej ziemi. Nie pożyczyłem [im] na lichwę ani oni na lichwę mnie nie pożyczali, a jednak każdy mi złorzeczy.
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
I PAN powiedział: Zapewniam, że będzie dobrze tym, którzy pozostaną. Sprawię, że wróg zatroszczy się o ciebie w czasie utrapienia i ucisku.
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
Czy [zwykłe] żelazo pokruszy żelazo z północy i stal?
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
Twoje bogactwo, Judo, i twoje skarby wydam na łup, bez opłaty, za wszystkie twoje grzechy we wszystkich twoich granicach.
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
I sprawię, że pójdziesz ze swymi wrogami do ziemi, której nie znasz. Rozpalił się bowiem ogień mojego gniewu i będzie płonąć nad wami.
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
Ty [mnie] znasz, PANIE, wspomnij i wejrzyj na mnie, a pomścij mnie wobec moich prześladowców. Nie porywaj mnie w swojej pobłażliwości [wobec nich]. Wiedz, że dla ciebie znoszę hańbę.
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
Gdy się znalazły twoje słowa, zjadłem je, a twoje słowo było dla mnie weselem i radością mego serca. Nazywam się bowiem twoim imieniem, PANIE, Boże zastępów!
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
Nie zasiadałem w radzie naśmiewców ani się [z nimi] nie radowałem; [ale] zasiadałem samotnie z powodu twojej surowej ręki, bo napełniłeś mnie gniewem.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
Czemu mój ból ma trwać wiecznie i moja rana ma być nieuleczalna, i nie chce się goić? Czy masz być dla mnie jak kłamca, [jak] wody zawodne?
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
Dlatego tak mówi PAN: Jeśli zawrócisz, wtedy zawrócę cię, abyś stał przede mną. I jeśli odłączysz to, co cenne, od tego, co nikczemne, będziesz jakby moimi ustami. Niech oni zawrócą do ciebie, ale ty nie zawracaj do nich.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
A uczynię cię dla tego ludu warownym murem spiżowym. Będą walczyć przeciwko tobie, ale cię nie przemogą, bo ja jestem z tobą, aby cię wybawić i ocalić, mówi PAN.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
Wyrwę cię z rąk niegodziwców i odkupię cię z rąk okrutników.

< Jeremiah 15 >