< Jeremiah 15 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
آنگاه خداوند به من فرمود: «حتی اگر موسی و سموئیل در حضور من می‌ایستادند و برای این قوم شفاعت می‌نمودند، بر ایشان ترحم نمی‌کردم. این قوم را از نظرم دور کن تا بروند.
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
اگر از تو بپرسند که به کجا بروند، از جانب من بگو که آنکه محکوم به مرگ است، به سوی مرگ؛ آنکه محکوم است با شمشیر کشته شود، به سوی شمشیر؛ آنکه محکوم است با قحطی هلاک گردد، به سوی قحطی و آنکه محکوم به اسیری است به سوی اسارت و بردگی!
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
من چهار هلاک کننده بر آنان خواهم فرستاد: شمشیر، تا آنان را بکشد؛ سگان، تا آنان را بدرند؛ لاشخورها، تا آنان را بخورند؛ و حیوانات وحشی، تا آنان را تکه پاره کنند.
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
«به سبب کارهای بدی که منسی، پسر حِزِقیا، پادشاه یهودا در اورشلیم کرد، ایشان را به چنان مجازات سختی خواهم رساند که مردم دنیا از سرنوشتشان وحشت نمایند!
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
«ای اهالی اورشلیم، چه کسی دیگر دلش به حال شما می‌سوزد؟ چه کسی برای شما گریه و زاری می‌کند؟ چه کسی حتی حاضر می‌شود به خود زحمت بدهد تا احوالتان را جویا شود؟
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
شما مرا ترک کرده و از من روگردانده‌اید، پس من نیز دست خود را دراز می‌کنم تا شما را نابود کنم، چون دیگر از رحم کردن به شما خسته شده‌ام!
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
کنار دروازه‌های شهرهایتان، شما را غربال خواهم کرد. فرزندانتان را از شما گرفته، نابودتان خواهم ساخت، چون نمی‌خواهید از گناه دست بردارید.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
شمار بیوه زنانتان مانند ریگهای ساحل زیاد خواهد شد؛ به هنگام ظهر، مردان جوان را کشته و مادرانشان را داغدار خواهم ساخت؛ کاری خواهم کرد که وحشت ناگهانی همهٔ آنها را فرا گیرد.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
مادری که صاحب هفت فرزند می‌باشد از غصه دق می‌کند، چون تمام پسرانش کشته خواهند شد؛ خورشید زندگی او به‌زودی غروب می‌کند! او بی‌اولاد و رسوا خواهد شد! هر که را زنده باقی مانده باشد به دم شمشیر خواهم سپرد!»
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
گفتم: «وای که چه مرد بدبختی هستم! ای کاش مادرم مرا به دنیا نیاورده بود! به هر جا که می‌روم، باید با همه مباحثه و مجادله کنم؛ نه به کسی پول به نزول داده‌ام، نه از کسی پول به نزول گرفته‌ام، با وجود این همه نفرینم می‌کنند!»
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
خداوند فرمود: «یقین بدان آینده‌ات نیکو خواهد بود؛ مطمئن باش که دشمن را وادار خواهم ساخت که به هنگام گرفتاری و بدبختی از تو درخواست کمک نماید.
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
«کسی نمی‌تواند میله‌های آهنی را بشکند، بخصوص آهن سرزمینهای شمال را که با مفرغ مخلوط شده باشد؛ همین‌طور سرسختی این قوم را نیز کسی نمی‌تواند در هم بشکند! پس به سبب همهٔ گناهانشان در تمام این سرزمین، ثروت و گنجهایشان را به عنوان غنیمت به دست دشمن خواهم سپرد.
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
اجازه خواهم داد تا دشمنانشان ایشان را مانند برده به سرزمینی ببرند که قبلاً هرگز در آنجا نبوده‌اند؛ زیرا آتش خشم من شعله‌ور شده، ایشان را خواهد سوزاند!»
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
آنگاه عرض کردم: «خداوندا، تو می‌دانی به خاطر توست که این همه توهین و ناسزا می‌شنوم! پس مرا به یاد آور و از من مراقبت نما! انتقام مرا از آزاردهندگانم بگیر؛ نسبت به آنها آنقدر صبور نباش تا موفق شوند مرا بکشند.
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
آنچه به من تاب و تحمل می‌دهد، کلام توست که خوراک روح گرسنهٔ من است؛ کلام تو دل اندوهگین مرا شاد و خرم می‌سازد. ای خداوند لشکرهای آسمان، چه افتخار بزرگی است که نام تو را بر خود دارم!
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
در ضیافتهای مردم خوشگذران شرکت نکرده‌ام بلکه به دستور تو به تنهایی نشسته از به یاد آوردن گناهان ایشان از خشم لبریز می‌شوم.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
چرا درد من دائمی است؟ چرا زخمهای من التیام نمی‌یابند؟ آیا می‌خواهی مرا ناامید کنی و برای جان تشنهٔ من، سراب باشی؟»
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
خداوند جواب داد: «سخنان بیهوده مگو؛ سخنان سنجیده بر زبان بران! فقط زمانی خواهم گذاشت پیام‌آور من باشی که نزد من بازگردی و به من توکل نمایی؛ در آن صورت به جای آنکه آنها بر تو تأثیر بگذارند، تو بر آنها تأثیر خواهی گذاشت.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
همان‌گونه که تسخیر شهری با دیوارهای محکم میسر نیست، من نیز تو را در برابر آنها مانند دیواری از مفرغ خواهم ساخت؛ آنها با تو خواهند جنگید، اما پیروز نخواهند شد، چون من با تو هستم تا از تو دفاع کنم و رهایی‌ات دهم.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
بله، من تو را از چنگ این اشخاص بدکار بیرون می‌کشم و از شر این مردم سنگدل نجات می‌دهم.»

< Jeremiah 15 >