< Jeremiah 15 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
INkosi yasisithi kimi: Loba bekumi phambi kwami oMozisi loSamuweli, inhliziyo yami ibingebe kulababantu; baxotshe phambi kwami, bayekele baphume.
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
Kuzakuthi-ke uba besithi kuwe: Sizaphuma siye ngaphi? Uzabatshela-ke uthi: Itsho njalo iNkosi: Abokufa baya ekufeni, labenkemba baya enkembeni, labendlala baya endlaleni, labokuthunjwa baya ekuthunjweni.
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
Ngoba ngizabamisela izinhlobo ezine, itsho iNkosi: Inkemba yokubulala, lezinja zokudonsa, lenyoni zamazulu lezinyamazana zomhlaba zokudla lezokubhubhisa.
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
Ngizabanikela babe yinto eyesabekayo kuyo yonke imibuso yomhlaba, ngenxa kaManase indodana kaHezekhiya, inkosi yakoJuda, ngalokho akwenza eJerusalema.
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
Ngoba ngubani ozakuhawukela, wena Jerusalema? Njalo ngubani ozakulilela? Njalo ngubani ozaphambukela eceleni ukubuza ngokuthula kwakho?
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
Wena ungidelile, itsho iNkosi, wabuyela emuva; ngakho ngizakwelula isandla sami ngimelene lawe, ngikuchithe; ngikhathele yikuhawukela.
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
Njalo ngizabela ngoluthi lokwela emasangweni elizwe; ngizabemuka abantwana, ngibhubhise abantu bami; kabaphendukanga endleleni zabo.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
Abafelokazi babo bandile kimi kuletshebetshebe lolwandle. Ngilethe phezu kwabo, phezu kukanina, ijaha, umchithi emini enkulu; ngiwisele phezu kwabo uvalo lezesabiso bengananzelele.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
Owazala abayisikhombisa usekhathele; usephefumule okokucina; ilanga lakhe litshone kusesemini; waba lenhloni, wayangeka; lensali yabo ngizayinikela enkembeni phambi kwezitha zabo, itsho iNkosi.
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
Maye mina, mama, ukuthi ungizele, umuntu wokuphikisana lomuntu wokuxabana emhlabeni wonke! Kangebolekisanga ngenzuzo, futhi kabangebolekisanga ngenzuzo, kanti bayangithuka, ngulowo lalowo wabo.
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
INkosi yathi: Isibili kuzakuba kuhle ngensali yakho; isibili ngizakuncengela esitheni ngesikhathi sokubi langesikhathi sosizi.
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
Insimbi ingayephula yini insimbi evela enyakatho lethusi?
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
Inotho yakho lokuligugu kwakho ngizakunikela kube yimpango, kungelantengo, langenxa yezono zakho zonke, ngitsho emingceleni yakho yonke.
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
Ngizakwenza ukuthi udlule kanye lezitha zakho uye elizweni ongalaziyo; ngoba umlilo ubasiwe olakeni lwami; uzabhebha phezu kwenu.
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
Wena uyazi, Nkosi; ngikhumbula, ungihambele, ungiphindiselele kwabangizingelayo; ungangisusi ekubekezeleni kwakho; yazi ukuthi ngenxa yakho ngithwele ihlazo.
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
Amazwi akho atholakala njalo ngawadla; lelizwi lakho kimi laba yinjabulo njalo laba yintokozo yenhliziyo yami; ngoba ibizo lakho labizwa phezu kwami, wena Nkosi, Nkulunkulu wamabandla.
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
Kangihlalanga emhlanganweni wabahleka usulu, kumbe ngijabule; ngenxa yesandla sakho ngahlala ngedwa; ngoba ungigcwalise ngentukuthelo.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
Kungani ubuhlungu bami bube khona njalonjalo, lenxeba lami lingelapheki, lisala ukuphola? Isibili uzakuba njengomqambimanga kimi yini, njengamanzi angathembekanga?
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
Ngakho itsho njalo iNkosi: Uba ubuya, ngizakubuyisa, ume phambi kwami; njalo uba ukhupha okuligugu kokungasizi lutho, uzakuba njengomlomo wami. Bona kababuyele kuwe, kodwa wena ungabuyeli kubo.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
Ngoba ngizakwenza ube ngumduli wethusi ovikelweyo kulababantu; njalo bazakulwa bemelene lawe, kodwa kabayikukwehlula, ngoba mina ngilawe ukukusindisa lokukophula, itsho iNkosi.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
Ngizakophula esandleni sababi, ngikuhlenge esandleni sabalesihluku.

< Jeremiah 15 >