< Jeremiah 15 >
1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
Et le Seigneur me dit: Quand même Moïse et Samuël comparaîtraient devant ma face, mon âme n'est pas pour ce peuple; chasse-le et qu'il s'en aille.
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
Et s'ils te disent: Où irons-nous? réponds, voici ce que dit le Seigneur: Vous irez les uns à la peste, les autres au glaive, d'autres à la famine, d'autres à la captivité, autant que ces fléaux en pourront frapper.
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
Et je les punirai de quatre manières, dit le Seigneur; il y aura le glaive pour égorger, les chiens pour déchirer, les bêtes de la terre et les oiseaux du ciel pour dévorer et consumer.
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
Et je les livrerai, pour leur affliction, à toutes les nations de la terre, à cause de Manassès, fils d'Ézéchias, roi de Juda, et de tout ce qu'il a fait dans Jérusalem?
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
Qui t'épargnera, Jérusalem? Qui craindra de te punir? Qui se penchera vers toi pour te rendre la paix.
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
Tu t'es détournée. de moi, dit le Seigneur, tu as reculé loin de moi; et j'étendrai la main sur toi, et je te détruirai, et je ne leur donnerai pas de rémission.
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
Et je les disperserai de toutes parts; aux portes mêmes de mon peuple, ils ont été privés de leurs enfants; ils ont perdu mon peuple par leurs méchancetés.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
Les veuves chez eux ont été multipliées plus que le sable du rivage. J'ai en plein midi envoyé le malheur sur les fils et sur les mères; et la ville, soudain je l'ai frappée de trouble et de terreur.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
Celle qui avait sept enfants en est privée; son âme a défailli; son soleil s'est couché au milieu du jour; elle a été confondue et maudite. Ce qui reste d'eux, je le livrerai au glaive en face de leurs ennemis.
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
Hélas! ma mère, pourquoi m'avez-vous enfanté, pour être un homme de contradiction par toute la terre? Je n'ai été utile à personne, et personne ne m'a été utile; la force m'a manqué contre ceux qui me maudissent.
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
Soit, Maître, qu'ils aient raison contre moi si je ne me suis tenu auprès de vous au temps de leurs calamités et au temps de leur tribulation, pour les servir contre leurs ennemis.
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
En vain le fer est connu de toi, en vain un vêtement d'airain
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
est ta force; je livrerai tes trésors au pillage sur ton territoire entier pour prix de tous tes péchés,
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
Et je t'asservirai à tes ennemis d'alentour, en une terre que tu ne connaissais pas; car le feu de ma colère est allumé, et il vous brûlera.
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
Seigneur, souvenez-vous de moi et visitez-moi; protégez-moi contre ceux qui me poursuivent, et ne tardez pas; sachez que c'est à cause de vous que je suis outragé
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
Par ceux qui tiennent pour rien votre parole; exterminez-les, et votre parole fera mes délices et la joie de mon cœur, parce que j'ai été appelé de votre nom, Seigneur tout-puissant.
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
Je ne me suis point assis dans leur assemblée quand ils vous raillaient; mais j'ai été saisi de crainte en face de votre main; je me suis assis solitaire, parce que j'étais rempli d'amertume.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
Pourquoi ceux qui m'affligent ont-ils prévalu sur moi? Ma blessure est profonde: comment en guérirai-je? me voici comme dans une eau trompeuse, à laquelle on ne peut se fier.
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
A cause de cela, voici ce que dit le Seigneur: Si tu reviens toujours à moi, je te fortifierai, et tu resteras debout devant ma face; et si tu sépares le bien du mal, tu seras comme ma bouche, et ils reviendront à toi, sans que tu reviennes à eux.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
Et je te donnerai contre ce peuple une défense et un rempart d'airain; et ils te combattront et ne pourront rien contre toi, parce que je suis avec toi pour te sauver
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
Et te retirer des mains des méchants, et je te rachèterai de la main des hommes de pestilence.