< Jeremiah 15 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
Yahweh me répondit: Quand Moïse et Samuel se tiendraient devant moi, mon âme ne se tournerait pas vers ce peuple; chasse-les de devant ma face et qu’ils partent!
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
Et s’ils te disent: « Où irons-nous? » tu leur diras: Ainsi parle Yahweh: Celui qui est pour la mort, à la mort; celui qui est pour l’épée, à l’épée; celui qui est pour la famine, à la famine; et celui qui est pour la captivité, à la captivité.
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
Et je susciterai contre eux quatre familles de fléaux, — oracle de Yahweh: l’épée pour tuer, les chiens pour déchirer, les oiseaux du ciel et les bêtes de la terre pour dévorer et pour détruire.
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
J’en ferai un objet d’horreur pour tous les royaumes de la terre, à cause de Manassé, fils d’Ezéchias, roi de Juda, pour ce qu’il a fait dans Jérusalem.
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
Qui donc aura pitié de toi, Jérusalem? qui se lamentera sur toi? Qui se détournera de sa route pour s’informer de ton état?
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
Tu m’as repoussé, — oracle de Yahweh, pour te retirer en arrière; et je vais étendre ma main sur toi pour te faire périr; je suis las d’avoir pitié.
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
Je les vannerai avec le van, aux portes du pays; je priverai d’enfants, je ferai périr mon peuple; ils ne reviennent pas de leurs voies.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
Ses veuves seront plus nombreuses que le sable de la mer. Je leur amènerai, sur la mère du jeune guerrier, le dévastateur en plein midi; je ferai fondre soudain sur elle l’angoisse et l’épouvante.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
La mère des sept fils se sent défaillir, elle va rendre l’âme; son soleil se couche pendant qu’il est jour encore; elle est confuse, couverte de honte. Ceux qui resteront, je les livrerai à l’épée devant leurs ennemis, oracle de Yahweh.
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
Malheur à moi, ô ma mère, parce que tu m’as enfanté, pour être un homme de dispute et de querelle pour tout le pays. Je n’ai rien prêté, et ils ne m’ont rien prêté, et tous me maudissent. —
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
Yahweh dit: Oui, je t’affermirai pour ton bien; certainement j’amènerai ton ennemi à te supplier, au temps du malheur et de la détresse.
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
Le fer brisera-t-il le fer du nord et l’airain?
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
Je livrerai tes biens et tes trésors au pillage, sans paiement, pour tous tes péchés et sur tout ton territoire;
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
et je les ferai passer avec tes ennemis dans un pays que tu ne connais pas; car un feu s’est allumé dans ma colère; il brûlera sur vous.
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
Tu le sais, Yahweh! Souviens-toi de moi, prends soin de moi et venge-moi de mes persécuteurs; ne m’enlève pas, dans ta patience envers eux, sache que c’est pour toi que je porte l’opprobre!
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
Dès que tes paroles se sont présentées, je les ai dévorées; elles sont devenues ma joie, et l’allégresse de mon cœur; car ton nom a été invoqué sur moi, Yahweh, Dieu des armées.
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
Je ne me suis pas assis dans l’assemblée des rieurs, pour m’y livrer à la gaieté; sous ta main, je me suis assis solitaire, car tu m’avais rempli de courroux.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
Pourquoi ma souffrance est-elle sans fin, et ma plaie douloureuse, rebelle à la guérison? Serais-tu pour moi comme un ruisseau trompeur, comme des eaux sur lesquelles on ne peut compter?
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
C’est pourquoi Yahweh parle ainsi: Si tu reviens vers moi, je te ferai revenir, pour que tu te tiennes devant ma face; et si tu sépares ce qui est précieux de ce qui est vil, tu seras comme ma bouche; ils reviendront vers toi, et ce n’est pas toi qui reviendras vers eux.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
Je ferai de toi, pour ce peuple, une forte muraille d’airain; ils te feront la guerre, mais ils ne pourront rien sur toi; car je serai avec toi pour te secourir et te délivrer, — oracle de Yahweh.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
Je te délivrerai de la main des méchants, et je te rachèterai de la main des violents.

< Jeremiah 15 >