< Jeremiah 15 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
Then Yahweh said [this] to me: “Even if Moses and Samuel could [come back from their graves and] and stand in front of me [and plead with me for these Israeli people], I would not act mercifully [IDM] toward these people. [I would tell you], ‘Send them away from me. Cause them to leave me!’
2 Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
And if they ask you, ‘Where shall we go?’, tell them, ‘This is what Yahweh says: The ones that I say must die, will die: The ones that I say must die in wars [MTY], will die in wars. The ones that I say must die from hunger, will die from hunger. The ones that I say must be captured [and taken to other countries], will be captured [and taken to other countries].
3 “Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
I will send four things that will get rid of them: I will send [enemy soldiers using] swords to kill them. I will send wild dogs to drag away [their corpses]. I will send vultures to eat [their corpses]. And I will send [other] wild animals to eat what remains [of their corpses].
4 N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
Because of [the wicked things that] King Manasseh did in Jerusalem, I will cause [people in] all the kingdoms of the earth to be horrified about [what will happen in Judah to] my people.
5 “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
You [people of], no one will [RHQ] feel sorry for you. No one will [RHQ] weep/cry for you. No one will [RHQ] ask (how you are/if you are well).
6 O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
You people have abandoned me; you have continued to walk away [from me] [DOU]. So, I will lift up my fist to smash you; I will not act mercifully toward you any longer.
7 Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
At the gates of your cities, I will [scatter you like a farmer scatters the chaff from his grain by] (winnowing it/throwing it up to allow the wind to blow the chaff away) [MET]. You, my people, have refused to turn away from your evil behavior. [So], I will get rid of you, and I will even cause your children to be killed.
8 Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
I will cause there to be more widows [in Judah] than [there are grains of] sand on the seashore [HYP]. At noontime, [when people will not be expecting it to happen], I will cause [an enemy army] to attack you, an army that will destroy your young men and cause their mothers to weep. I will cause you to suddenly experience great suffering/pain and become very terrified.
9 Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
A woman who has seven children will become faint and (gasp for breath/be hardly able to breathe); [it will be as though] daylight will become darkness for her, [because most of] her children will be dead, and she will be disgraced and humiliated [DOU]. And her children who are still alive, I will enable your enemies to kill them. [That will surely happen because I], Yahweh, have said it.’”
10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
[I said to] my mother, “I am very sad; I wish that you had not given birth to me; everyone in this land opposes me and quarrels with me. I am not a person who lends [money to people and threatens to sue/harm them if they do not pay me back when they should], and I am not a person who borrows [money from others and then refuses to pay it back], but everyone [HYP] curses me.”
11 Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
But Yahweh replied to me, “[Jeremiah], I will take care of you. And at times when your enemies have troubles and disasters, they will [come to you and] plead for you [to help them].”
12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
[Yahweh also told me to say to the people] of Judah, “Your enemies, who are [as strong as] iron or bronze, [will attack you] from the north; no one will be able to stop them.
13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
I will give all the valuable possessions [of the people of Judah] to their enemies, without them paying for it. Their valuable possessions will be the payment/reward [that I will give them] because of all the sins that you have committed throughout your country.
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
I will tell your enemies to force you to become their prisoners, and to take you to other lands that you do not [even] know about, and force you to become their slaves. [That will happen] because I am extremely angry [with you]; my being angry is [like] [SIM] a fire that will burn forever.”
15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
[Then I said], “Yahweh, you know [what is happening to me]. [Please] come and (help me/take care of me). Punish those who are (persecuting me/causing me to suffer). [Please] do not continue to be patient with them and do not allow me to die now. It is (for your sake/because I serve you) that I am suffering.
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
Yahweh my God, you are the Commander of the armies of angels; and when you spoke to me, I was delighted with your message; it caused me to be joyful, and I eagerly accepted [MET] what you said because I belong to you. [IDM, MTY]
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
When the people were carousing together, I never joined them; I sat alone, because you [MTY] are the one who controls what I do. I was very angry [with those people because of their sins].
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
So, (why do you [allow] me to continue to suffer?/I do not understand why you allow me to continue to suffer.) [RHQ] It seems that [RHQ] my wounds cannot be healed. [Sometimes you help me, sometimes you do not help me]. It seems that you are as undependable as a brook that has water in it only during certain seasons; you are like a spring that has dried up.”
19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
Then Yahweh [replied], “If you begin again to [trust in] me, I will restore you, in order that you can continue to serve me. If you proclaim good/valuable messages and not worthless ones, you will continue to be the one who speaks what I tell you to say. You must cause the people to pay attention to what you say; you must not pay attention to what they say.
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
They will fight against you, but I will protect you, like [SIM] people are protected from their enemies by a bronze wall. They will not defeat you, because I will be with you, and I will protect and rescue [DOU] you.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”
[Truly], I will keep you safe from those wicked people, I will rescue you when you are seized by cruel people. [That will happen because I], Yahweh, have said it.”

< Jeremiah 15 >