< Jeremiah 14 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
Cuvântul DOMNULUI care a venit la Ieremia referitor la secetă.
2 “Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
Iuda jelește și porțile acestuia lâncezesc; ele sunt negre până la pământ; și strigătul Ierusalimului s-a înălțat.
3 Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
Și nobilii lor au trimis pe cei mici ai lor la ape; ei au ajuns la gropi și nu au găsit apă; s-au întors cu vasele lor goale; au fost rușinați și încurcați și și-au acoperit capetele.
4 Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
Pentru că pământul este crăpat, pentru că nu a fost ploaie pe pământ, plugarii s-au rușinat, și-au acoperit capetele.
5 Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
Da, cerboaica a născut în câmp și și-a părăsit puii, pentru că nu era iarbă.
6 Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
Și măgarii sălbatici au stat pe înălțimi, au adulmecat vântul ca dragonii; ochii li s-au sfârșit, pentru că nu era iarbă.
7 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
DOAMNE, deși nelegiuirile noastre mărturisesc împotriva noastră, fă tu aceasta pentru numele tău, pentru că decăderile noastre sunt multe; noi am păcătuit împotriva ta.
8 Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
O, speranța lui Israel, salvatorul acestuia în timp de tulburare, de ce să fii tu ca un străin în țară și ca un călător care se abate să găzduiască pentru o noapte?
9 Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
De ce să fii ca un om înmărmurit, ca un bărbat puternic care nu poate salva? Totuși tu, DOAMNE, ești în mijlocul nostru și noi ne numim după numele tău; nu ne lăsa.
10 Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
Astfel spune DOMNUL către acest popor: Bine le-a plăcut să rătăcească, nu și‑au oprit picioarele, de aceea DOMNUL nu îi primește; își va aminti acum nelegiuirea lor și va cerceta păcatele lor.
11 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
Atunci DOMNUL mi-a spus: Nu te ruga pentru acest popor pentru binele lor.
12 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
Când vor posti nu le voi asculta strigătul; și când ei aduc ofrandă arsă și un dar, nu le voi primi; ci îi voi mistui cu sabie și cu foamete și cu ciumă.
13 Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
Atunci am spus: Ah, Doamne DUMNEZEULE! Iată, profeții le spun: Nu veți vedea sabia, nici nu veți avea foamete; ci vă voi da pace sigură în acest loc.
14 Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
Atunci DOMNUL mi-a spus: Profeții profețesc minciuni în numele meu; nu eu i-am trimis, nici nu le-am poruncit, nici nu le-am vorbit; ei vă profețesc o viziune falsă și ghicire și un lucru de nimic și înșelăciunea inimii lor.
15 Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
De aceea astfel spune DOMNUL referitor la profeții care profețesc în numele meu și pe care eu nu i-am trimis, totuși ei spun: Nu va fi sabie și foamete în această țară. Prin sabie și foamete vor fi acei profeți mistuiți.
16 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Și poporul către care ei profețesc va fi aruncat pe străzile Ierusalimului din cauza foametei și a sabiei; și nu vor avea pe nimeni să îi îngroape pe ei, pe soțiile lor, pe fiii lor sau pe fiicele lor, pentru că voi vărsa stricăciunea lor asupra lor.
17 “Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
De aceea tu să le spui acest cuvânt: Ochii mei să curgă cu lacrimi noapte și zi și să nu înceteze, pentru că fiica fecioară a poporului meu este zdrobită cu o mare spărtură, cu o lovitură foarte apăsătoare.
18 Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
Dacă ies la câmp, atunci, iată, pe cei uciși cu sabia! Și dacă intru în cetate, atunci, iată, pe cei care sunt bolnavi de foamete! Da, deopotrivă profetul și preotul vor merge într-o țară pe care nu o cunosc.
19 Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
Ai respins tu în întregime pe Iuda? a detestat sufletul tău Sionul? De ce ne-ai lovit și nu este vindecare pentru noi? Am căutat pace și nu este nici[un] bine; și un timp de vindecare și, iată, tulburare!
20 Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Recunoaștem, DOAMNE, stricăciunea noastră și nelegiuirea părinților noștri, pentru că noi am păcătuit împotriva ta.
21 Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
Nu ne detesta, pentru numele tău, nu dezonora tronul gloriei tale; amintește-ți, nu rupe legământul tău cu noi.
22 Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
Sunt printre deșertăciunile neamurilor vreunii care pot să dea ploaie? Sau pot cerurile să dea averse de ploi? Nu ești tu acela, DOAMNE Dumnezeul nostru? De aceea noi te vom aștepta, pentru că tu ai făcut toate acestea.

< Jeremiah 14 >