< Jeremiah 14 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
خداوند دربارهٔ خشکسالی یهودا به ارمیا چنین فرمود:
2 “Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
«سرزمین یهودا عزادار است؛ زندگی و جنب و جوش از شهرها رخت بربسته؛ مردم همه ماتم زده‌اند و صدای آه و ناله‌شان از اورشلیم به گوش می‌رسد.
3 Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
ثروتمندان خدمتکاران خود را برای آوردن آب به سر چاهها می‌فرستند، اما چاهها همه خشک است؛ پس ناامید و سرافکنده، دست خالی باز می‌گردند.
4 Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
کشاورزان مأیوس و غمگینند، چون باران نباریده و زمین، خشک شده و ترک خورده است!
5 Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
در بیابان، آهو بچه‌اش را به حال خود رها می‌کند، چون علوفه نمی‌یابد.
6 Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
گورخرها نیز روی تپه‌های خشک می‌ایستند و مثل شغالهای تشنه، نفس‌نفس می‌زنند و در جستجوی علف، چشمانشان را خسته می‌کنند، ولی چیزی برای خوردن نمی‌یابند.»
7 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
ای خداوند، اگرچه گناهان ما، ما را محکوم می‌سازند، ولی به خاطر عزت نام خود ما را یاری نما! ما بسیار از تو دور شده‌ایم و در حق تو گناه کرده‌ایم.
8 Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
ای امید اسرائیل، ای کسی که در تنگنا و گرفتاری نجا‌ت‌دهندۀ مایی، چرا مثل غریبی که از سرزمین ما رد می‌شود و مسافری که شبی نزد ما می‌ماند، نسبت به ما بیگانه گردیده‌ای؟
9 Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
آیا تو هم درمانده شده‌ای؟ آیا مانند جنگجوی ناتوانی گردیده‌ای که کاری از او ساخته نیست؟ خداوندا، تو در میان مایی و ما نام تو را بر خود داریم و قوم تو هستیم؛ پس ای خداوند، ما را به حال خود رها نکن!
10 Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
ولی خداوند به این قوم چنین جواب می‌دهد: «شما خود دوست داشتید از من دور شوید و سرگردان گردید، و هیچ کوشش نکردید احکام مرا بجا آورید. پس من نیز، دیگر شما را نمی‌پذیرم. تمام کارهای بدتان را به یاد آورده، به سبب گناهانتان شما را مجازات خواهم نمود.»
11 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
خداوند به من گفت: «از این پس از من نخواه که این قوم را یاری نمایم و برکت دهم.
12 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
حتی اگر روزه بگیرند، به دادشان نخواهم رسید؛ اگر هم هدیه و قربانی بیاورند، نخواهم پذیرفت؛ بلکه ایشان را با جنگ و قحطی و وبا هلاک خواهم کرد!»
13 Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
آنگاه گفتم: «خداوندا، انبیایشان می‌گویند که نه جنگ می‌شود، نه قحطی! آنها به مردم می‌گویند که تو به ایشان صلح و آرامش پایدار می‌بخشی.»
14 Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
خداوند فرمود: «این انبیا به نام من به دروغ نبوّت می‌کنند؛ من نه آنها را فرستاده‌ام و نه پیامی به ایشان داده‌ام؛ رؤیاهای آنان از جانب من نیست، بلکه آنان از سحر و جادو و تخیل دلهای فریبکار خود با شما سخن می‌گویند.
15 Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
من این انبیای فریبکار را که به نام من پیام می‌آورند مجازات خواهم کرد، زیرا من به ایشان سخنی نگفته‌ام. آنها می‌گویند که نه جنگ می‌شود نه قحطی، پس ایشان را در جنگ و قحطی هلاک خواهم ساخت!
16 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
و این قوم که به این پیشگویی‌ها گوش می‌دهند، به همان‌گونه کشته خواهند شد و نعشهایشان در کوچه‌های اورشلیم خواهند افتاد و کسی باقی نخواهد ماند تا جنازه‌ها را دفن کند؛ زن و شوهر، دختر و پسر، همه از بین خواهند رفت، زیرا من آنها را به سبب گناهانشان مجازات خواهم نمود.
17 “Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
«پس با ایشان دربارهٔ اندوه خود سخن بران و بگو:”شب و روز از چشمانم اشک غم جاری است و آرام و قرار ندارم، چون هموطنانم به دم تیغ افتاده‌اند و روی زمین در خون خود می‌غلتند.
18 Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
اگر به صحرا بروم، نعش کسانی را می‌بینم که به ضرب شمشیر کشته شده‌اند؛ و اگر به شهر بروم با کسانی روبرو می‌شوم که در اثر گرسنگی و بیماری در حال مرگند؛ هم انبیا و هم کاهنان به سرزمینی بیگانه برده شده‌اند.“»
19 Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
قوم اسرائیل می‌گویند: «ای خداوند، آیا یهودا را کاملاً ترک کرده‌ای؟ آیا از اهالی اورشلیم بیزار شده‌ای؟ چرا ما را آنچنان زده‌ای که هیچ درمانی برایمان نباشد؟ ما منتظر بودیم که شفایمان بدهی، ولی چنین نشد؛ در انتظار صلح و آرامش بودیم، اما اضطراب و ترس ما را فرا گرفت!
20 Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
ای خداوند، ما به شرارت خود و گناه اجدادمان اعتراف می‌کنیم. بله، ما در حق تو گناه کرده‌ایم.
21 Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
خداوندا، به خاطر نام خودت ما را طرد نکن و اورشلیم، جایگاه استقرار تخت پر شکوهت را ذلیل و خوار مساز. عهدی را که با ما بستی به یاد آور و آن را نشکن!
22 Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
آیا بت می‌تواند باران عطا کند؟ و یا آسمان می‌تواند به خودی خود باران بباراند؟ ای یهوه خدای ما، چه کسی جز تو می‌تواند چنین کارهایی را به انجام رساند؟ از این رو ما، تنها به تو امید بسته‌ایم!»

< Jeremiah 14 >