< Jeremiah 14 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
Az Úrnak szava, a mit Jeremiásnak szólott a szárazság felől:
2 “Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
Gyászol Júda, és kapui roskadoznak; szomorkodnak a földön, és Jeruzsálem kiáltása felszáll.
3 Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
Fejedelmeik is kiküldik gyermekeiket vízért: elmennek a kútakig, nem találnak vizet; visszatérnek üres edényekkel; szégyenkeznek és pironkodnak, és befedik fejöket.
4 Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
A föld miatt, a mely retteg, mert nem esett eső a földön, szégyenkeznek a szántóvetők, és befedik fejöket.
5 Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
Még a szarvas-üsző is megellik a mezőn, és ott hagyja fiát, mert nincsen fű.
6 Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
A vadszamarak pedig a sziklához állanak, levegő után kapkodnak, mint a tengeri szörnyek, szemeik eltikkadnak, mert nincs fű.
7 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Ha bűneink ellenünk tanúskodnak: cselekedjél Uram a te nevedért, mert temérdek a mi törvényszegésünk; vétkeztünk ellened!
8 Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
Izráel reménysége, megszabadítója a nyomorúság idején! Miért vagy e földön úgy, mint valami jövevény és mint valami utas, a ki éjjeli szállásra tér be?
9 Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
Miért vagy olyan, mint a megriasztott férfi; mint a vitéz, a ki nem tud segíteni? Hiszen te közöttünk vagy, Uram, és mi a te nevedről neveztetünk; ne hagyj el minket!
10 Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
Ezt mondja az Úr e népnek: Úgy szerettek ide-oda futkározni, lábaikat meg nem tartóztatták! Azért az Úr nem kedvelte őket. Most megemlékezik az ő bűnökről, és vétkeikért megfenyíti őket.
11 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
És mondá nékem az Úr: Ne könyörögj e népért, az ő javára.
12 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
Mikor bőjtölnek, én meg nem hallgatom kiáltozásukat, és ha égőáldozatot vagy ételáldozatot készítenek, nem lesznek kedvesek előttem; sőt fegyverrel, éhséggel és döghalállal irtom ki őket.
13 Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
És mondék: Ah, Uram Isten! Hiszen a próféták mondják vala nékik: Fegyvert nem láttok, éhség sem lesz rajtatok, sőt állandó békességet adok néktek ezen a helyen.
14 Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
És monda az Úr nékem: Hazugságot prófétálnak a próféták az én nevemben; nem küldtem őket, nem parancsoltam nékik, nem is beszéltem velök; hazug látomást, varázslást, hiábavalóságot és szívbeli csalárdságot jövendölnek néktek.
15 Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
Azért ezt mondja az Úr a próféták felől, a kik az én nevemben prófétálnak, holott én nem küldtem őket és mégis azt mondják: fegyver és éhség nem lesz e földön: Fegyver és éhség miatt vesznek el azok a próféták!
16 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
A nép pedig, a melynek ők prófétálnak, ott hever majd Jeruzsálem utczáin az éhség és a fegyver miatt, és nem lesz, a ki eltemesse őket, őket és feleségeiket, fiaikat és leányaikat; így zúdítom rájok gonoszságukat!
17 “Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
Azért e szavakat mondjad nékik: Szemeim könyeket hullatnak éjjel és nappal, és nem szünnek meg; mert nagy rontással rontatott meg a szűz, az én népemnek leánya, igen fájdalmas vereséggel.
18 Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
Ha kimegyek a mezőre, hát ímé fegyver által levágottak; ha bemegyek a városba, hát ímé éhség miatt elepedtek vannak ott! Bizony próféta is, pap is olyan földre költöznek, a melyet nem ismernek!
19 Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
Egészen elvetetted-é Júdát, avagy a Siont útálja-é lelked? miért vertél úgy meg, hogy semmi orvosságunk se legyen? Békességet vártunk, de nincs semmi jó; és gyógyulásnak idejét, de ímé, itt van a rettegés!
20 Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Ismerjük Uram a mi gonoszságainkat, atyáink bűnét; bizony vétkeztünk ellened!
21 Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
Ne vesd meg a te nevedért; ne gyalázd meg a te dicsőségednek székét! Emlékezzél; ne rontsd meg a te velünk való szövetségedet!
22 Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
Vannak-é a pogányok bálványai között, a kik esőt adhatnak? És ad-é záporokat az ég? Avagy nem te vagy-é a mi Urunk Istenünk, és nem benned kell-é bíznunk, hiszen te cselekedted mindezt!