< Jeremiah 14 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
Khokhahaih kawng pongah Jeremiah khaeah Angraeng ih lok hae tiah angzoh.
2 “Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
Judah loe palungset moe, khongkhanawk doeh angpho o boeh; prae to qah o haih, Jerusalem qahhaih lok loe ranui bangah caeh tahang.
3 Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
Angraengnawk mah a tamnanawk to tuidok hanah patoeh; nihcae loe tuikung ah caeh o, toe tui om ai; tuiduenawk doeh akok ah amlaem o haih let; lu to a khuk o moe, azathaih hoiah oh o sut.
4 Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
Prae thungah kho angzo ai boeh pongah, long to akah; lawkphrawk kaminawk doeh azathaih tong o pongah, lu to a khuk o.
5 Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
Ue, tasuk doeh taw ah acaa tapen, toe phroh om ai pongah, acaa to pahnawt sut boeh.
6 Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
Taw ih hrangnawk doeh hmuensangnawk ah angdoet o moe, tasuinawk baktiah takhi to hroek o; phroh caak han om ai pongah, mikmaeng o boeh.
7 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Aw Angraeng, hnuk amlaem kami ka pop o parai boeh; na koeh ai ih zaehaih to ka sak o moeng boeh pongah, ka zae o haih mah misa ah omsak cadoeh, na hmin hoiah na loisak ah.
8 Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
Aw Israel kaminawk oephaih, raihaih tong naah pahlongkung, tipongah prae thungah angvin baktiah na oh o moe, qumto khue iih hanah kholong caeh angvin baktiah na oh loe?
9 Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
Tipongah poek anghmang sut kami baktih, pahlong thai ai thacak kami baktiah na oh loe? Aw Angraeng, nang loe kaicae salakah na oh, kaicae loe na hmin hoi kawk ih kami ah ni ka oh o, na caeh taak hmah!
10 Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
Angraeng mah hae kaminawk khaeah, Nihcae loe amhet han koeh o, khok to pakaa o ai, to pongah Angraeng mah nihcae to talawk ai; nihcae kasae sakhaih to vaihi poek ueloe, a sak o ih zaehaih baktih toengah lokcaek tih, tiah thuih.
11 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
To pacoengah Angraeng mah kai khaeah, Hae kaminawk khosak hoih hanah lawkthui pae hmah.
12 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
Buhzah hoi lawkthui o cadoeh, nihcae hanghaih lok to ka tahngai pae mak ai; hmai angbawnhaih hoiah tangqum paek o naah doeh, ka talawk pae mak ai; nihcae to sumsen, khokhahaih hoi kasae nathaih hoiah kam rosak han, tiah a thuih.
13 Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
Toe kai mah, Ah, Angraeng Sithaw, khenah, tahmaanawk mah nihcae khaeah, sumsen hoi raihaih na tong o mak ai, khokhahaih doeh na tong o mak ai; boeng thai ai monghaih to hae ahmuen ah kang paek o han, tiah a thuih pae o bae, tiah ka naa.
14 Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
To naah Angraeng mah kai khaeah, tahmaanawk loe kai ih ahmin hoiah amsawnlok to thuih o; kai mah nihcae to patoeh ai, lok ka paek ai, lok doeh ka thui pae ai; nihcae loe amsawn hnuksakhaih, taqawk ih ahmin hoiah tahmaahaih to sak o moe, atho om ai hmuen, angmacae poekhaih baktiah ni, alinghaih lok to ang thuih o.
15 Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
To pongah Angraeng mah anih ih ahmin hoiah lokthui tahmaanawk kawng pongah hae tiah thuih; Kai mah nihcae to patoeh ai, toe nihcae mah prae thungah sumsen hoi khokhahaih pha mak ai, tiah thuih o; to tahmaanawk loe sumsen hoi khokhahaih hoiah dueh o tih.
16 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Tahmaanawk mah lokthuih pae ih kaminawk loe sumsen hoi khokhahaih pongah, Jerusalem loklamnawk ah va o sut tih; nihcae ih qok, a zunawk, capanawk hoi canunawk ih qok to aphum hanah kami mi doeh om mak ai; a sak o ih zaehaih hoi katingah nihcae nuiah ka phaksak han.
17 “Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
Nihcae khaeah, Kai kaminawk ih canu kacuem tangla loe, kanung parai nganbawh kana to zok o moe, ahuhnawk doeh angkhaeh o boeh pongah, ka mikkhraetui hae khoving khodai, boeng ai ah long nasoe.
18 Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
Lawk ah ka caeh naah doeh, sumsen hoi hum ih kaminawk to ka hnuk; vangpui thungah ka kun naah doeh, khokha pongah nganna kaminawk to ka hnuk; ue, tahmaa hoi qaima loe panoek vai ai ih prae ah caeh hoi boeh, tiah thui paeh, tiah ang naa.
19 Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
Judah to na pahnawt ving boeh maw? Na hinghaih mah Zion to hnukma boeh maw? Kaicae ngatuihaih om ai maw, tipongah patang nang khangsak loe? Monghaih to ka zing o, toe kahoih hmuen roe om ai; ngantuihaih ka zing o naah, raihaih ka hnuk o lat!
20 Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Aw Angraeng, na nuiah ka zae o boeh moe, ka set o haih hoiah kam panawk ih zaehaih to ka panoek o boeh.
21 Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
Na hmin pongah, kaicae hae hnuma hmah, na lensawkhaih to ahmin saesak hmah; kaicae hoi na sak ih lokmaihaih to pahnet hmah loe, phrae doeh phrae hmah.
22 Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
Gentel kaminawk mah bok o ih tidoeh avang ai krangnawk thungah kho angzosak thaih krang oh o maw? To tih ai boeh loe vannawk mah kho angzoh o sak thaih maw? Kho angzosak thaih loe, Aw Angraeng, kaicae ih Sithaw, Nang na ai maw? To pongah nang to kang zing o han; hae hmuennawk boih loe nangmah sak ih hmuen ah ni oh o.

< Jeremiah 14 >