< Jeremiah 13 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ kí o sì ra àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀, kí o sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí omi kí ó kàn án.”
Tako mi govori Gospod: »Pojdi in si priskrbi lanen pas in ga daj na svoja ledja, v vodo pa ga ne daj.«
2 Bẹ́ẹ̀ ni mo ra àmùrè gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí, mo sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ mi.
Tako sem dobil pas glede na Gospodovo besedo in si ga nadel na ledja.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá nígbà kejì,
Gospodova beseda je drugič prišla k meni, rekoč:
4 “Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fiwé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Perati, kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta.”
»Vzemi pas, ki si ga dobil, ki je na tvojih ledjih in vstani, pojdi k Evfratu in ga tam skrij v skalno luknjo.«
5 Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Perati gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.
Tako sem odšel in ga skril pri Evfratu, kakor mi je Gospod zapovedal.
6 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi, “Lọ sí Perati kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀.”
Po mnogih dneh se je pripetilo, da mi je Gospod rekel: »Vstani, pojdi k Evfratu in vzemi od tam pas, ki sem ti ga tam zapovedal skriti.«
7 Nígbà náà ni mo lọ sí Perati mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.
Potem sem odšel k Evfratu in kopál ter vzel pas iz kraja, kjer sem ga skril. Glej, pas je bil iznakažen, ni bil koristen za nič.
8 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Potem je prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
9 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Juda àti ìgbéraga ńlá ti Jerusalẹmu.
»Tako govori Gospod: ›Na ta način bom oškodoval Judov ponos in velik ponos Jeruzalema.
10 Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.
To zlo ljudstvo, ki zavrača poslušati moje besede, ki hodijo v zamisli svojega srca in hodijo za drugimi bogovi, da jim služijo in da jih obožujejo, bodo torej kakor ta pas, ki ni dober za nič.
11 Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Israẹli àti gbogbo ilé Juda mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’
Kajti kakor se pas trdno drži moževih ledij, tako sem storil, da se me trdno drži celotna Izraelova hiša in celotna Judova hiša, ‹ govori Gospod, ›da mi bodo lahko za ljudstvo, za ime, za hvalo in za slavo. Toda nočejo slišati.
12 “Sọ fún wọn, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, gbogbo ìgò ni à ó fi ọtí wáìnì kún.’ Bí wọ́n bá sì sọ fún ọ pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìgò ni ó yẹ láti bu ọtí wáìnì kún?’
Zato jim boš govoril to besedo: ›Tako govori Gospod, Izraelov Bog: ›Vsak meh bo napolnjen z vinom.‹ Rekli ti bodo: ›Mar ne vemo zagotovo, da bo vsak meh napolnjen z vinom?‹
13 Nítorí náà sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò fi ìmutípara kún gbogbo olùgbé ilẹ̀ yìí pẹ̀lú ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì gbogbo àwọn tó ń gbé ní Jerusalẹmu.
Potem jim boš rekel: ›Tako govori Gospod: ›Glejte, s pijanostjo bom napolnil vse prebivalce te dežele, celo kralje, ki sedijo na Davidovem prestolu, duhovnike, preroke in vse prebivalce [prestolnice] Jeruzalem.
14 Èmi yóò ti èkínní lu èkejì, àwọn baba àti ọmọkùnrin pọ̀ ni Olúwa wí. Èmi kì yóò dáríjì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú, èmi kì yóò ṣe ìyọ́nú láti máa pa wọ́n run.’”
Treščil jih bom enega ob drugega, celo očete in sinove skupaj, ‹ govori Gospod. ›Ne bom se usmilil niti prizanašal niti imel usmiljenja, temveč jih uničim.‹«
15 Gbọ́ kí o sì fetísílẹ̀, ẹ má ṣe gbéraga, nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Poslušajte in pazljivo prisluhnite. Ne bodite ponosni, kajti Gospod je govoril.
16 Ẹ fi ògo fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ó tó mú òkùnkùn wá, àti kí ó tó mú ẹsẹ̀ yín tàsé lórí òkè tí ó ṣókùnkùn. Nígbà tí ẹ̀yin sì ń retí ìmọ́lẹ̀, òun yóò sọ ọ́ di òjìji yóò sì ṣe bi òkùnkùn biribiri.
Dajte slavo Gospodu, svojemu Bogu, preden povzroči temo in preden se vaša stopala spotaknejo na temnih gorah in medtem ko gledate za svetlobo, jo obrne v smrtno senco in jo naredi [za] veliko temo.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fetísílẹ̀, Èmi yóò sọkún ní ìkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín. Ojú mi yóò sun ẹkún kíkorò, tí omi ẹkún, yóò sì máa sàn jáde, nítorí a kó agbo Olúwa lọ ìgbèkùn.
Toda če tega ne boste poslušali, bo moja duša jokala na skrivnih krajih zaradi vašega ponosa. Moje oko bo hudo jokalo in teklo s solzami, ker je bil Gospodov trop ujet odveden.
18 Sọ fún ọba àti ayaba pé, “Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀, ẹ sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ yín, adé ògo yín bọ́ sí ilẹ̀ láti orí yín.”
»Reci kralju in kraljici: ›Ponižajta se, usedita se, kajti vajine kneževine bodo propadle, celó krona vajine slave.
19 Àwọn ìlú tí ó wà ní gúúsù ni à ó tì pa, kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti ṣí wọn. Gbogbo Juda ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn, gbogbo wọn ni a ó kó lọ ní ìgbèkùn pátápátá.
Južna mesta bodo zaprta in nihče jih ne bo odprl. Ves Juda bo odveden v ujetništvo, v celoti bo odveden v ujetništvo.‹
20 Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá. Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà; àgùntàn tí ò ń mú yangàn.
Povzdigni svoje oči in poglej tiste, ki prihajajo iz severa. Kje je trop, ki ti je bil dan, tvoj krasen trop?
21 Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹ àwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà. Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọ bí aboyún tó ń rọbí?
Kaj boš rekla, ko te bo kaznoval? Kajti učila si jih, da so poveljniki in kakor vodja nad teboj. Ali te ne bodo zajele bolesti kakor žensko v porodnih mukah?
22 Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè, “Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?” Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀ ni aṣọ rẹ fi fàya tí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.
Če rečeš v svojem srcu: ›Zakaj so prišle nadme te stvari?‹ Zaradi veličine tvoje krivičnosti so odkriti krajci tvojih oblačil in tvoje pete so razgaljene.
23 Ǹjẹ́ Etiopia le yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.
Mar lahko Etiopijec spremeni svojo kožo ali leopard svoje lise? Potem bi lahko tudi vi delali dobro, ki ste navajeni, da delate zlo.
24 “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbò tí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.
Zato jih bom razkropil kakor strnišče, ki ga odnaša veter iz divjine.
25 Èyí ni ìpín tìrẹ; tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,” ni Olúwa wí, “Nítorí ìwọ ti gbàgbé mi o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.
To je tvoj žreb, delež tvojih zmožnosti od mene, ‹ govori Gospod; ›ker si me pozabila in zaupala v neresnico.
26 N ó sí aṣọ lójú rẹ, kí ẹ̀sín rẹ le hàn síta—
Zato bom odkril krajce tvojih oblačil nad tvojim obrazom, da se lahko prikaže tvoja sramota.
27 ìwà àgbèrè àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, àìlójútì panṣágà rẹ! Mo ti rí ìwà ìríra rẹ, lórí òkè àti ní pápá. Ègbé ni fún ọ ìwọ Jerusalẹmu! Yóò ti pẹ́ tó tí o ó fi máa wà ní àìmọ́?”
Videl sem tvoja zakonolomstva in tvoja rezgetanja, nespodobnost tvojega vlačugarstva in tvoje ogabnosti na hribih polj. Gorje ti, oh [prestolnica] Jeruzalem! Mar ne boš očiščena? Kdaj bo to enkrat prišlo?‹«

< Jeremiah 13 >