< Jeremiah 13 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ kí o sì ra àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀, kí o sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí omi kí ó kàn án.”
Így szólt hozzám az Örökkévaló: Menj és vegyél magadnak len-övet és tedd azt derekadra, de a vízbe ne tedd.
2 Bẹ́ẹ̀ ni mo ra àmùrè gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí, mo sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ mi.
Megvettem az övet az Örökkévaló igéje szerint és derekamra tettem.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá nígbà kejì,
És lett hozzám az Örökkévaló igéje másodszor, mondván:
4 “Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fiwé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Perati, kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta.”
Vedd az övet, melyet megvettél, amely a derekadon van, és kelj fel, menj Perátba és dugd ott el egy sziklahasadékban.
5 Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Perati gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.
Elmentem és eldugtam Perátban, amint megparancsolta nekem az Örökkévaló.
6 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi, “Lọ sí Perati kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀.”
És volt sok idő múlva, szólt hozzám az Örökkévaló: Kelj föl, menj Perátba és vesd el onnan az övet, amelyről parancsoltam neked, hogy ott eldugjad.
7 Nígbà náà ni mo lọ sí Perati mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.
Elmentem Perátba, ástam és elvettem az övet azon helyről, ahova eldugtam volt; és íme elromlott az öv, nem volt semmire sem alkalmas.
8 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
9 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Juda àti ìgbéraga ńlá ti Jerusalẹmu.
Így szól az Örökkévaló: Ekképpen fogom lerontani Jehúda büszkeségét és Jeruzsálem nagy büszkeségét.
10 Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.
Ez a rossz nép, akik vonakodnak szavaimra hallgatni, akik járnak szívük makacssága szerint és jártak más istenek után azokat szolgálva és leborulva előttük – olyan legyen, mint ez az öv, mely semmire sem alkalmas.
11 Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Israẹli àti gbogbo ilé Juda mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’
Mert valamint kapcsolódik az öv a férfi derekához, úgy kapcsoltam magamhoz Izrael egész házát és Jehúda egész házát, úgymond az Örökkévaló, hogy legyenek nekem népül és hírnevül, dicsőségül és díszül; de nem hallgattak rá.
12 “Sọ fún wọn, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, gbogbo ìgò ni à ó fi ọtí wáìnì kún.’ Bí wọ́n bá sì sọ fún ọ pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìgò ni ó yẹ láti bu ọtí wáìnì kún?’
És mondjad nekik ezt az igét: Így szól az Örökkévaló, Izrael Istene; minden tömlő megtelik borral. Ők meg szólnak majd hozzád: vajon nem tudjuk-e jól, hogy minden tömlő borral telik meg?
13 Nítorí náà sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò fi ìmutípara kún gbogbo olùgbé ilẹ̀ yìí pẹ̀lú ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì gbogbo àwọn tó ń gbé ní Jerusalẹmu.
Akkor szólj hozzájuk: Így szól az Örökkévaló: íme én megtöltöm mind ez ország lakóit meg a királyokat, akik a Dávid trónján ülnek és a papokat és a prófétákat és mind a Jeruzsálem lakóit részegséggel.
14 Èmi yóò ti èkínní lu èkejì, àwọn baba àti ọmọkùnrin pọ̀ ni Olúwa wí. Èmi kì yóò dáríjì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú, èmi kì yóò ṣe ìyọ́nú láti máa pa wọ́n run.’”
És összecsapom őket, egyiket a másikához, az apákat és a gyermekeket egyetemben, úgymond az Örökkévaló; nem könyörülök és nem kímélek és nem irgalmazok, hogy meg ne rontsam őket.
15 Gbọ́ kí o sì fetísílẹ̀, ẹ má ṣe gbéraga, nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Halljátok és figyeljetek, ne büszkélkedjetek, mert az Örökkévaló beszélt.
16 Ẹ fi ògo fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ó tó mú òkùnkùn wá, àti kí ó tó mú ẹsẹ̀ yín tàsé lórí òkè tí ó ṣókùnkùn. Nígbà tí ẹ̀yin sì ń retí ìmọ́lẹ̀, òun yóò sọ ọ́ di òjìji yóò sì ṣe bi òkùnkùn biribiri.
Adjátok az Örökkévalónak, a ti Istenteknek, tiszteletet, mielőtt besötétednék és mielőtt megütköznének lábaitok az alkonyat hegyein és ti reméltek világosságot, de ő homállyá teszi, sűrű köddé fordítja.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fetísílẹ̀, Èmi yóò sọkún ní ìkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín. Ojú mi yóò sun ẹkún kíkorò, tí omi ẹkún, yóò sì máa sàn jáde, nítorí a kó agbo Olúwa lọ ìgbèkùn.
De ha nem halljátok, rejtekben sír a lelkem a gőgössége miatt: könnyezve könnyezik és könnytől szétfolyik szemem, mert fogságba került az Örökkévaló nyája.
18 Sọ fún ọba àti ayaba pé, “Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀, ẹ sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ yín, adé ògo yín bọ́ sí ilẹ̀ láti orí yín.”
Mondd a királynak és az uralkodónőnek: Alacsonyra üljetek, mert leesett fejetekről díszes koronátok.
19 Àwọn ìlú tí ó wà ní gúúsù ni à ó tì pa, kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti ṣí wọn. Gbogbo Juda ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn, gbogbo wọn ni a ó kó lọ ní ìgbèkùn pátápátá.
A Délvidék városai elzárattak és senki sem nyitja ki, számkivetésbe vitetett egész Jehúda, számkivetésbe vitetett teljesen.
20 Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá. Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà; àgùntàn tí ò ń mú yangàn.
Emeljétek fel szemeiteket és lássátok az északról jövőket! Hol a nyáj, mely neked adatott, díszes juhaid?
21 Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹ àwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà. Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọ bí aboyún tó ń rọbí?
Mit fogsz mondani, midőn majd fölédrendeli, akiket társaknak szoktattál magadhoz fejekül; nemde fájdalmak fognak el, mint a szülő asszonyé?
22 Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè, “Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?” Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀ ni aṣọ rẹ fi fàya tí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.
És ha azt mondod szívedben: miért értek engem ezek? Bűnöd nagyságáért takartattak fel uszályaid, bántalmaztattak sarkaid.
23 Ǹjẹ́ Etiopia le yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.
Vajon megváltoztatja-e kúsita a bőrét és párduc a foltjait? Ti is tudnátok jót tenni, ti gonosztevéshez szokottak!
24 “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbò tí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.
Elszórom tehát őket, mint az elszálló polyvát a puszta szelének.
25 Èyí ni ìpín tìrẹ; tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,” ni Olúwa wí, “Nítorí ìwọ ti gbàgbé mi o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.
Ez a te sorsod, kimért osztályrészed én tőlem, úgymond az Örökkévaló, mivel megfeledkeztél rólam és hazugságban bíztál.
26 N ó sí aṣọ lójú rẹ, kí ẹ̀sín rẹ le hàn síta—
Fel is takartam tehát uszályaidat arcod fölé, hogy megláttassék gyalázatod.
27 ìwà àgbèrè àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, àìlójútì panṣágà rẹ! Mo ti rí ìwà ìríra rẹ, lórí òkè àti ní pápá. Ègbé ni fún ọ ìwọ Jerusalẹmu! Yóò ti pẹ́ tó tí o ó fi máa wà ní àìmọ́?”
Házasságtöréseidet és nyerítéseidet, paráználkodásod galádságát a halmokon, a mezőn láttam undokságaidat: jaj neked Jeruzsálem, nem fogsz megtisztulni – még meddig nem?

< Jeremiah 13 >