< Jeremiah 13 >
1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ kí o sì ra àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀, kí o sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí omi kí ó kàn án.”
[One day] Yahweh said to me, “Go and buy a linen waistcloth. Put it on, but do not wash it.”
2 Bẹ́ẹ̀ ni mo ra àmùrè gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí, mo sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ mi.
So I bought a [very nice] waistcloth, which is what Yahweh told me to do, and I put it on.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá nígbà kejì,
Then [later] Yahweh gave me another message.
4 “Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fiwé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Perati, kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta.”
He said, “Go to the small Perath Stream [near Jerusalem] and hide your waistcloth in a crevice/hole in the rocks.”
5 Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Perati gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.
So I went to the stream and did what Yahweh told me to do.
6 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi, “Lọ sí Perati kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀.”
A long time later, Yahweh said to me, “Go [back] to that stream and get the waistcloth that I told you to hide there.”
7 Nígbà náà ni mo lọ sí Perati mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.
So I went to the Perath Stream and dug out the waistcloth from the crevice/hole in which I had hidden it. But it was ruined, and useless.
8 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Then Yahweh gave me this message:
9 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Juda àti ìgbéraga ńlá ti Jerusalẹmu.
“[What happened to your waistcloth] shows that I will destroy the things that [the people of] Jerusalem and [other places in] Judah are very proud of.
10 Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.
Those wicked people refuse to pay attention to what I say. They stubbornly do just what they desire to do; they worship other gods. Therefore, they will become completely useless, like your waistcloth.
11 Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Israẹli àti gbogbo ilé Juda mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’
Just like a waistcloth clings closely/tightly to a man’s waist, I wanted the people [MTY] of Israel and Judah to cling closely to me. I wanted them to be my people, people who would praise me and honor me. But they would not pay attention [to me]. “
12 “Sọ fún wọn, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, gbogbo ìgò ni à ó fi ọtí wáìnì kún.’ Bí wọ́n bá sì sọ fún ọ pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìgò ni ó yẹ láti bu ọtí wáìnì kún?’
“[So], tell this to them: ‘Yahweh, the God whom you Israeli [people worship], says that every leather wineskin should be filled with wine.’ And [when you tell that to them], they will reply, ‘(Of course/Certainly) we know [RHQ] that all wineskins should be filled with wine!’
13 Nítorí náà sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò fi ìmutípara kún gbogbo olùgbé ilẹ̀ yìí pẹ̀lú ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì gbogbo àwọn tó ń gbé ní Jerusalẹmu.
And then you must tell them, ‘No, that is not what Yahweh means. What he said means that he will cause this land to be filled with people who are drunk. [That will include all of you]—the king who sits on the throne that King David previously sat on, the priests and the prophets, and even the common people of Jerusalem.’
14 Èmi yóò ti èkínní lu èkejì, àwọn baba àti ọmọkùnrin pọ̀ ni Olúwa wí. Èmi kì yóò dáríjì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú, èmi kì yóò ṣe ìyọ́nú láti máa pa wọ́n run.’”
[He is saying], ‘I will cause you to bash each other. [Even] parents will bash their children. I will not pity you or act mercifully toward you at all; pitying you will not prevent me from getting rid of you.’”
15 Gbọ́ kí o sì fetísílẹ̀, ẹ má ṣe gbéraga, nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
[You people of Judah], pay very careful attention [DOU]. Do not be proud, because Yahweh has spoken to you.
16 Ẹ fi ògo fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ó tó mú òkùnkùn wá, àti kí ó tó mú ẹsẹ̀ yín tàsé lórí òkè tí ó ṣókùnkùn. Nígbà tí ẹ̀yin sì ń retí ìmọ́lẹ̀, òun yóò sọ ọ́ di òjìji yóò sì ṣe bi òkùnkùn biribiri.
[It is as though] he is ready to bring darkness on you and to cause you to stumble and fall [as you walk] on the hills when it is becoming dark. [So] praise/honor Yahweh your God before that happens. If you do not do that, you will look for light, but all you will see is darkness and gloom.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fetísílẹ̀, Èmi yóò sọkún ní ìkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín. Ojú mi yóò sun ẹkún kíkorò, tí omi ẹkún, yóò sì máa sàn jáde, nítorí a kó agbo Olúwa lọ ìgbèkùn.
And if you [still] refuse to heed what he says, [what will happen to you because of] your being proud will cause me to cry when I am alone. My eyes will be filled with tears because [you], Yahweh’s people, [whom he takes care of like a shepherd takes care of] [MET] his flock, will [all] be [captured by your enemies and] taken to other countries.
18 Sọ fún ọba àti ayaba pé, “Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀, ẹ sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ yín, adé ògo yín bọ́ sí ilẹ̀ láti orí yín.”
[You people of Judah], say to the king and to his mother, “Come down from sitting on your thrones and [humbly] sit in the dust, because [your enemies] will soon snatch from your heads your glorious crowns.”
19 Àwọn ìlú tí ó wà ní gúúsù ni à ó tì pa, kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti ṣí wọn. Gbogbo Juda ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn, gbogbo wọn ni a ó kó lọ ní ìgbèkùn pátápátá.
The towns in the southern part of Judah will be surrounded by your enemies, and no one will be able to get through their lines [to rescue the people in those towns]. [You people of] Judah will be captured and taken away; you will all be (exiled/taken [to foreign countries)].
20 Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá. Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà; àgùntàn tí ò ń mú yangàn.
[You leaders of Jerusalem], open your eyes and look: [The enemy armies are ready to] march down from the north. [When that happens], what will happen to [RHQ] the [people of Judah who are like] a beautiful flock of sheep, people that he gave to you to take care of?
21 Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹ àwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà. Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọ bí aboyún tó ń rọbí?
What will you say [RHQ] when Yahweh appoints people from other countries to rule over you, people who you [mistakenly] thought were your friends? You will [RHQ] suffer very much pain, like a woman who is about to give birth to a baby.
22 Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè, “Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?” Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀ ni aṣọ rẹ fi fàya tí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.
You will ask yourselves, “Why is this happening to us?” [I will reply that] it is because of your many sins. That is why [soldiers of the invading armies] will lift up the skirts [of your women] and rape them.
23 Ǹjẹ́ Etiopia le yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.
A man from Ethiopia certainly cannot [RHQ] change the color of his [black] skin, and a leopard certainly cannot [RHQ] change its spots. Similarly, you cannot start doing what is good, because you have always done what is evil.
24 “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbò tí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.
[Yahweh says], “I will scatter you like chaff that is blown away by the wind from the desert.
25 Èyí ni ìpín tìrẹ; tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,” ni Olúwa wí, “Nítorí ìwọ ti gbàgbé mi o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.
That is what is certainly going to happen to you; the things that I have determined will happen to you, because you have forgotten me, and you are trusting in false [gods].
26 N ó sí aṣọ lójú rẹ, kí ẹ̀sín rẹ le hàn síta—
[It is as though] I myself will pull your skirts up over your faces and cause you to be very ashamed because everyone will be able to see your sex organs.
27 ìwà àgbèrè àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, àìlójútì panṣágà rẹ! Mo ti rí ìwà ìríra rẹ, lórí òkè àti ní pápá. Ègbé ni fún ọ ìwọ Jerusalẹmu! Yóò ti pẹ́ tó tí o ó fi máa wà ní àìmọ́?”
I have seen that you [act like men who are eager to commit adultery]; you are like male horses that whinny when they desire [to have sex with] a female horse. I have seen that you worship disgusting idols in the fields and on the hills. [You people of] Jerusalem, terrible things will happen to you! How long will it be [RHQ] until you are acceptable to me [again]?”