< Jeremiah 12 >

1 Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkígbà, nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá. Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ. Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé? Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
Sprawiedliwy jesteś, PANIE, choćbym się z tobą spierał. Ja jednak będę rozmawiać z tobą o [twoich] sądach. Czemu szczęści się droga bezbożnych? [Czemu] spokojnie żyją wszyscy, którzy postępują bardzo zdradliwie?
2 Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀, wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso. Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn, o jìnnà sí ọkàn wọn.
Zasadziłeś ich, zapuścili też korzenie; rosną i nawet wydają owoc. Bliski jesteś ich ust, ale daleki od ich nerek.
3 Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa, o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò. Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa. Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
Ale ty, PANIE, znasz mnie, wypatrujesz mnie i doświadczyłeś moje serce, [i wiesz], że jest z tobą. Odłącz ich jak owce na rzeź i przygotuj ich na dzień zabicia.
4 Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà, tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ? Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀. Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé, “Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”
Jak długo ziemia będzie płakać, a trawa na wszystkich polach będzie usychać z powodu niegodziwości jej mieszkańców? Giną wszystkie zwierzęta i ptactwo, bo mówią: Nie widzi naszego końca.
5 Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré, tí àárẹ̀ sì mú ọ, báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje? Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà, bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé, kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
Jeśli biegłeś z pieszymi i zmęczyłeś się, to jak zmierzysz się z końmi? A jeśli [zmęczyłeś się] w spokojnej ziemi, w której pokładałeś nadzieję, co zrobisz przy wezbraniu Jordanu?
6 Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ìdílé ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ, wọ́n ti hó lé ọ lórí. Má ṣe gbà wọ́n gbọ́ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.
Nawet twoi bracia i dom twego ojca sprzeniewierzyli się tobie, oni też głośno wołają za tobą. Ale nie wierz im, choćby mówili do ciebie piękne słowa.
7 Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀, èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀. Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
Opuściłem swój dom, porzuciłem swoje dziedzictwo; umiłowaną mojej duszy wydałem w ręce jej wrogów.
8 Ogún mi ti rí sí mi bí i kìnnìún nínú igbó. Ó ń bú ramúramù mọ́ mi; nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
Moje dziedzictwo stało się dla mnie jak lew w lesie; podnosi przeciwko mnie swój głos, dlatego je znienawidziłem.
9 Ogún mi kò ha ti rí sí mi bí ẹyẹ kannakánná tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i? Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ, ẹ mú wọn wá jẹ.
Moje dziedzictwo jest pstrym ptakiem, ptaki dokoła będą przeciwko niemu. Chodźcie, zbierzcie wszystkie zwierzęta polne, zejdźcie się na żer.
10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́, tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀; wọ́n ó sọ oko dídára mi di ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
Wielu pasterzy zniszczyło moją winnicę, zdeptało mój dział; mój rozkoszny dział zamienili w opustoszałe pustkowie.
11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀ tí kò wúlò níwájú mi, gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
Zamienili go w pustkowie; a spustoszony leży w żałobie przede mną; cała ziemia pustoszeje, bo nikt tego nie bierze [sobie] do serca.
12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀ ni àwọn apanirun ti gorí, nítorí idà Olúwa yóò pa láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà; kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
Na wszystkie pustynne wzniesienia przyjdą niszczyciele, bo miecz PANA pożre [wszystko] od jednego krańca do drugiego krańca ziemi. Żadne ciało nie będzie miało pokoju.
13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká, wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn. Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín, nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.
Posiali pszenicę, ale będą zbierać ciernie; natrudzili się, ale nic nie osiągną. Zawstydzą się ze swoich plonów z powodu zapalczywego gniewu PANA.
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn.
Tak mówi PAN o wszystkich moich złych sąsiadach dotykających mojego dziedzictwa, które dałem w dziedzictwo memu ludowi Izraelowi: Oto wykorzenię ich z ich ziemi, a dom Judy wyrwę spośród nich.
15 Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù.
A gdy ich wyrwę, wrócę, zlituję się nad nimi i znowu przyprowadzę każdego z nich do jego dziedzictwa i każdego z nich do jego ziemi.
16 Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘Níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi.
I jeśli dokładnie się nauczą dróg mojego ludu, [i] będą przysięgać na moje imię, [mówiąc]: PAN żyje, podobnie jak nauczali mój lud przysięgać na Baala, wtedy zostaną zbudowani wśród mego ludu.
17 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.
Ale jeśli nie usłuchają, wtedy wykorzenię ten naród, wyrwę i wytracę go, mówi PAN.

< Jeremiah 12 >