< Jeremiah 12 >

1 Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkígbà, nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá. Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ. Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé? Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
Igaz vagy Uram, hogyha perlek is veled; éppen azért hadd beszélhessek veled peres kérdésekről! Miért szerencsés az istentelenek útja? Miért vannak békességben mindnyájan a hűtlenkedők?
2 Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀, wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso. Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn, o jìnnà sí ọkàn wọn.
Beplántálod őket, meg is gyökereznek; felnevekednek, gyümölcsöt is teremnek; közel vagy te az ő szájokhoz, de távol vagy az ő szívöktől!
3 Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa, o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò. Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa. Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
Engem pedig ismersz te, Uram! látsz engem, és megvizsgáltad irántad való érzésemet: szakítsd külön őket, mint a mészárszékre való juhokat, és készítsd őket a megölésnek napjára!
4 Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà, tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ? Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀. Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé, “Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”
Meddig gyászoljon a föld, és meddig száradjon el minden fű a mezőn? A benne lakók gonoszsága miatt pusztul el barom és madár; mert azt mondják: Nem látja meg a mi végünket!
5 Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré, tí àárẹ̀ sì mú ọ, báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje? Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà, bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé, kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
Hogyha gyalogokkal futsz, és elfárasztanak téged: mimódon versenyezhetnél a lovakkal? És ha csak békességes földön vagy bátorságban: ugyan mit cselekednél a Jordán hullámai között?
6 Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ìdílé ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ, wọ́n ti hó lé ọ lórí. Má ṣe gbà wọ́n gbọ́ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.
Bizony még a te atyádfiai és a te atyádnak háznépe is: ők is hűtlenül bántak veled; ők is tele torokkal kiabáltak utánad! Ne higyj nékik, még ha szépen beszélgetnek is veled!
7 Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀, èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀. Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
Elhagytam házamat; ellöktem örökségemet, ellenségének kezébe adtam azt, a kit lelkem szeret.
8 Ogún mi ti rí sí mi bí i kìnnìún nínú igbó. Ó ń bú ramúramù mọ́ mi; nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
Az én örökségem olyanná lett hozzám, mint az oroszlán az erdőben; ordítva támadt ellenem; ezért gyűlölöm őt.
9 Ogún mi kò ha ti rí sí mi bí ẹyẹ kannakánná tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i? Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ, ẹ mú wọn wá jẹ.
Tarka madár-é az én örökségem nékem? Nem gyűlnek-é ellene madarak mindenfelől? Jőjjetek, seregeljetek össze mind ti mezei vadak; siessetek az evésre!
10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́, tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀; wọ́n ó sọ oko dídára mi di ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
Sok pásztor pusztította az én szőlőmet, taposta az én osztályrészemet; az én drága örökségemet sivatag pusztává tették!
11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀ tí kò wúlò níwájú mi, gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
Pusztává tették, felém sír, mint puszta! Elpusztíttatik az egész föld, mert nincs senki, a ki eszére térjen.
12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀ ni àwọn apanirun ti gorí, nítorí idà Olúwa yóò pa láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà; kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
A pusztában levő minden magaslatra pusztítók érkeznek, mert az Úr fegyvere emészt a föld egyik szélétől a föld másik széléig; senkinek sem lesz békessége.
13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká, wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn. Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín, nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.
Búzát vetettek és tövist aratnak; fáradnak, de nem boldogulnak, és szégyent vallotok a ti jövedelmetekkel az Úr haragjának búsulása miatt.
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn.
Ezt mondja az Úr minden én gonosz szomszédom felől, a kik hozzányúlnak az én örökségemhez, a melyet örökségül adtam az én népemnek, Izráelnek: Ímé, én kigyomlálom őket az ő földükből, és Júda házát is kigyomlálom közülök!
15 Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù.
És azután, ha majd kigyomlálom őket, ismét könyörülök rajtok, és visszahozom őket, kit-kit az ő örökségébe, és kit-kit az ő földére.
16 Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘Níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi.
És ha megtanulják az én népemnek utait, és az én nevemre esküsznek ilyen módon: Él az Úr! a mint megtanították népemet megesküdni a Baálra: akkor felépülnek majd népem között.
17 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.
Ha pedig nem hallgatnak meg, akkor bizony kigyomlálom azt a népet, és elvesztem, azt mondja az Úr.

< Jeremiah 12 >