< Jeremiah 12 >

1 Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkígbà, nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá. Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ. Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé? Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
Atĩrĩrĩ, Wee Jehova ũtũũraga ũnduagĩra ciira na kĩhooto rĩrĩa rĩothe ndarehe ciira mbere yaku. No rĩrĩ, no nyende twaranĩrie nawe ũndũ ũkoniĩ kĩhooto gĩaku: Nĩ kĩĩ gĩtũmaga mũthiĩre wa mũndũ ũrĩa mwaganu ũgaacĩre? Nĩ kĩĩ gĩtũmaga andũ arĩa matarĩ wĩtĩkio matũũre megangarĩte?
2 Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀, wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso. Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn, o jìnnà sí ọkàn wọn.
Ũmahaandĩte, nao makagĩa na mĩri; makũraga na magaciara maciaro. Ũgwetagwo hĩndĩ ciothe nĩ tũnua twao, no meciiria ma ngoro ciao marĩ haraaya nawe.
3 Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa, o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò. Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa. Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
No rĩrĩ, Wee Jehova nĩũnjũũĩ; nĩwe ũnyonaga na ũkoiruuria meciiria makwa ũndũ ũgũkoniĩ. Maguucũrũrie ta ngʼondu irathiĩ gũthĩnjwo! Maamũre ũmetererie mũthenya wao wa kũũragwo!
4 Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà, tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ? Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀. Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé, “Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”
Nĩ ihinda rĩigana atĩa bũrũri ũgũtũũra ũngʼarĩte, nayo nyeki mĩgũnda-inĩ yothe ĩikare ĩhoohete? Tondũ andũ arĩa matũũraga kuo nĩ andũ aaganu-rĩ, nyamũ na nyoni nĩithirĩte. Ningĩ, andũ acio maroiga atĩrĩ, “Ndakoona ũrĩa tũkaarĩkĩrĩria.”
5 Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré, tí àárẹ̀ sì mú ọ, báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje? Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà, bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé, kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
“Angĩkorwo nĩũtengʼeranĩtie na andũ marathiĩ na magũrũ nao magakũhũmia-rĩ, wakĩhota atĩa gũcindana na mbarathi? Angĩkorwo nĩũhĩngagwo ũkĩgerera bũrũri ũrĩ thayũ-rĩ, ũgaakĩhota atĩa gũtũrĩkania ihinga iria irĩ hũgũrũrũ-inĩ cia Jorodani?
6 Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ìdílé ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ, wọ́n ti hó lé ọ lórí. Má ṣe gbà wọ́n gbọ́ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.
Ariũ a maitũguo, na andũ a nyũmba ya thoguo-rĩ, o nao nĩmagũkunyanĩire; nĩmanĩrĩire na mũgambo magũũkĩrĩre. Ndũkae kũmeehoka, o na mangĩaria wega waku atĩa.
7 Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀, èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀. Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
“Niĩ nĩngũtirika nyũmba yakwa, na ndiganĩrie igai rĩakwa; nĩngũneana ũrĩa nyendete moko-inĩ ma thũ ciake.
8 Ogún mi ti rí sí mi bí i kìnnìún nínú igbó. Ó ń bú ramúramù mọ́ mi; nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
Igai rĩakwa rĩtuĩkĩte ta mũrũũthi ũrĩ gĩthaka-inĩ harĩ niĩ. Nĩkũrarama ũndaramĩire, nĩ ũndũ ũcio ngaũthũũra.
9 Ogún mi kò ha ti rí sí mi bí ẹyẹ kannakánná tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i? Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ, ẹ mú wọn wá jẹ.
Githĩ igai rĩakwa rĩtituĩkĩte ta nyoni ndĩa-nyama ĩrĩ maroro harĩ niĩ, ĩrĩa nyoni iria ingĩ ndĩa-nyama ĩthiũrũrũkagĩria ikamĩtharĩkĩra? Thiĩ ũkonganie nyamũ ciothe cia gĩthaka; cirehe imatambuure.
10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́, tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀; wọ́n ó sọ oko dídára mi di ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
Arĩithi aingĩ nĩmakananga mũgũnda wakwa wa mĩthabibũ, na marangĩrĩrie mũgũnda wakwa; nĩmagatũma mũgũnda wakwa ũrĩa mwega ũtuĩke rũngʼũrĩ rũkirĩte ihooru.
11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀ tí kò wúlò níwájú mi, gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
Magaatũma gũkire ihooru, gũtuĩke kũndũ kũngʼaru na gũkirĩte ihooru maitho-inĩ makwa; bũrũri ũcio wothe nĩũgathũkangio nĩ ũndũ gũtirĩ mũndũ wakũũrũmbũiya.
12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀ ni àwọn apanirun ti gorí, nítorí idà Olúwa yóò pa láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà; kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
Werũ-inĩ guothe kũrĩa gũtũũgĩru aniinani nĩkuo makaiyũra, nĩgũkorwo rũhiũ rwa njora rwa Jehova nĩrũkaniinana kuuma gĩturi kĩmwe kĩa bũrũri nginya kĩrĩa kĩngĩ; gũtigakorwo mũndũ o na ũrĩkũ ũgaakorwo na thayũ.
13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká, wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn. Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín, nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.
Makaahandaga ngano, makagetha mĩigua; makeenogia na matione kĩndũ. Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, conokerai magetha manyu, tondũ wa marakara mahiũ ma Jehova.”
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn.
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Ha ũhoro wa andũ acio aaganu maandigiicĩirie, o acio matunyaga andũ akwa a Isiraeli igai rĩrĩa ndaamaheire-rĩ, nĩngamamunya kuuma mabũrũri mao, na munye nyũmba ya Juda yume gatagatĩ kao.
15 Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù.
No rĩrĩ, thuutha wa kũmamunya nĩngacooka ndĩmaiguĩre tha na njookie o ũmwe wao igai-inĩ rĩake mwene, bũrũri-inĩ wake kĩũmbe.
16 Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘Níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi.
Ningĩ mangĩkeruta wega mĩthiĩre ya andũ akwa na mehĩte makĩgwetaga rĩĩtwa rĩakwa moige atĩrĩ, ‘Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo,’ o ta ũrĩa maarutire andũ akwa hĩndĩ ĩmwe kwĩhĩta makĩgwetaga rĩĩtwa rĩa Baali-rĩ, hĩndĩ ĩyo nao nĩmakahaandwo marũme wega gatagatĩ ka andũ akwa.
17 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.
No rĩrĩ, rũrĩrĩ o na rũrĩkũ rũngĩkaaga kũnjigua-rĩ, nĩngarũmunya na mĩri na ndĩrũniine biũ,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.

< Jeremiah 12 >