< Jeremiah 11 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
LEUM GOD El fahk nu sik,
2 “Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
“Porongo kas ke wuleang uh. Fahk nu sin mwet Judah ac nu selos su muta Jerusalem
3 Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
lah nga, LEUM GOD lun Israel, fah selngawi mwet nukewa su tia akos kas in wuleang se inge —
4 Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
wuleang se su nga tuh orala yurin mwet matu lalos ke nga tuh usalosme liki acn Egypt, acn se ma oana funyu firirir se nu selos ah. Nga tuh fahk nu selos in akosyu ac in oru ma nukewa ma nga sapkin. Nga fahkang nu selos mu elos fin akos, elos ac fah mwet luk ac nga ac fah God lalos.
5 Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
Na nga fah akpwayei wuleang su nga tuh orala yurin mwet matu lalos mu nga ac sang nu selos facl mut ac kasrup fohk we se su elos muta fac inge.” Ac nga fahk, “Aok pwaye, LEUM GOD.”
6 Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
Na LEUM GOD El fahk nu sik, “Fahla nu in siti lun Judah ac nu inkanek Jerusalem ac sulkakin kas luk we. Fahk nu sin mwet uh in porongo kalmen kas in wuleang sac ac akos.
7 Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
Ke nga tuh use mwet matu lalos liki facl Egypt, nga wili na nu selos in akosyu, ac nga kalwenina in akesmakinyalos kac nwe misenge.
8 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
Tusruktu elos tiana porongo ku akosyu, a elos nukewa likkekelana ac oru na ma koluk. Nga sapkin elos in karinganang wuleang sac, a elos srunga. Ouinge nga use nu faclos mwe kalyai nukewa ma aketeyuki in wuleang uh.”
9 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
Na LEUM GOD El fahk nu sik, “Mwet Judah ac mwet Jerusalem elos orek pwapa koluk in lainyu.
10 Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
Elos sifilpa folokla nu ke ouiya koluk lun mwet matu lalos meet ah, su srunga oru ma nga fahk. Elos alu nu ke god saya. Israel ac Judah kewa kunausla wuleang ma nga tuh oru yurin mwet matu lalos.
11 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
Ouinge nga, LEUM GOD, akesmakinyalos lah nga ac fah use ongoiya lulap nu faclos, ac elos fah tia ku in kaingkunla. Elos fin mau wowoyak nu sik nga in kasrelos, nga ac fah tia lohngolos.
12 Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
Na mwet Judah ac Jerusalem fah som ac wowoyak nu ke god ma elos esukak mwe kisa keng nu se, tusruktu god ingan ac fah koflana molelosla ke pacl se ongoiya inge ac tuku uh.
13 Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
Oasr god puspis lun mwet Judah oana pisen siti lalos. Ac mwet Jerusalem elos etoak loang puspis in orek kisa nu sin Baal, god srungayuk sac, oana pisen inkanek in siti uh.
14 “Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
Jeremiah, nimet kom aol mwet inge in pre nu sik ku kwafe nu sik kaclos. Elos fin sun ongoiya ac pang in sukok kasru sik, nga ac tia porongalos.”
15 “Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
LEUM GOD El fahk, “Mwet su nga lungse yohk elos oru na ma koluk. Ya oasr suwohs lalos in muta in Tempul sik? Ya elos nunku mu elos ku in kutongya mwe ongoiya nu selos ke elos orek wulela ac ke elos kisakin kosro natulos? Ya elos ku in engan?
16 Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
Sie pacl ah nga pangon elos oana soko sak olive matol insroa ac rukruk ke fahko kato. A inge, ke sie ngirngir oana pusren pulal, nga fah esukak sra uh ac koteya lah kac uh.
17 Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
“Nga, LEUM GOD Kulana, pa tuh yukwiya Israel ac Judah. Tuh pa inge nga akkalemye nu selos lah elos ac sun ongoiya. Elos sifacna use ma inge nu faclos mweyen elos orekma koluk. Elos akkasrkusrakyeyu ke sripen elos orek kisa nu sel Baal.”
18 Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
LEUM GOD El akkalemye nu sik ke nunak sulallal ma mwet lokoalok luk elos oru lainyu.
19 Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
Nga oana soko sheep fusr ma tia etu lah ac utukla in anwuki — nga tiana etu lah pwapa koluk lalos uh ma nu sik. Elos fahk, “Lela kut in pakiya sak soko uh ke srakna moul. Kut in uniya tuh in wangin mwet sifil esamul.”
20 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
Na nga pre ac fahk, “O LEUM GOD Kulana, nununku lom uh suwohs. Kom srike ac etu nunak ac insien mwet. Nga filiyuwot nu inpoum, ouinge lela nga in liye ke kom ac oru foloksak nu sin mwet inge.”
21 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
Mukul Anathoth elos lungse nga in anwuki, ac elos fahkma nu sik lah elos ac uniyuwi nga fin tia tui in kaskas Inen LEUM GOD.
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Ouinge LEUM GOD Kulana El fahk, “Nga ac kalyaelos! Mukul fusr natulos ac fah anwuki ke mweun, ac tulik natulos ac fah misa ke masrinsral.
23 Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”
Nga oakiya pacl in ongoiya se tari nu fin mwet Anathoth, ac ke pacl sac tuku, wangin sie selos fah moul.”

< Jeremiah 11 >