< Jeremiah 11 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
The word that was maad of the Lord to Jeremye,
2 “Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
and seide, Here ye the wordis of this couenaunt, and speke ye to the men of Juda, and to the dwelleris of Jerusalem; and thou schalt seie to hem,
3 Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
The Lord God of Israel seith these thingis, Cursid be the man that herith not the wordis of this couenaunt,
4 Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
which Y comaundide to youre fadris, in the dai in which Y ledde hem out of the lond of Egipt, fro the irone furneis; and Y seide, Here ye my vois, and do ye alle thingis whiche Y comaundide to you, and ye schulen be in to a puple to me, and Y schal be in to God to you;
5 Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
that Y reise the ooth which Y swoor to youre fadris, that Y schulde yyue to hem a lond flowynge with mylk and hony, as this dai is. And Y answeride, and seide, Amen, Lord.
6 Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
And the Lord seide to me, Crye thou alle these wordis in the citees of Juda, and with out Jerusalem, and seie thou, Here ye the wordis of this couenaunt, and do ye tho;
7 Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
for Y witnessynge haue witnessid to youre fadris, in the dai in which Y ledde hem out of the lond of Egipt, `til to this dai; Y roos eerli, and witnesside, and seide, Here ye my vois.
8 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
And thei herden not, nether bowiden doun her eere, but thei yeden forth ech man in the schrewidnesse of his yuel herte; and Y brouyte in on hem alle the wordis of this couenaunt, which Y comaundide that thei schulden do, and thei diden not.
9 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
And the Lord seide to me, Sweryng togidere is foundun in the men of Juda, and in the dwelleris of Jerusalem;
10 Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
thei turneden ayen to the formere wickidnessis of her fadris, that nolden here my wordis; and therfor these men yeden aftir alien goddis, for to serue hem; the hous of Israel and the hous of Juda maden voide my couenaunt, which Y made with the fadris of hem.
11 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
Wherfor the Lord seith these thingis, Lo! Y schal bringe in on hem yuels, of whiche thei schulen not mow go out; and thei schulen crie to me, and Y schal not here hem.
12 Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
And the citees of Juda and the dwellers of Jerusalem schulen go, and schulen crye to hem, to whiche thei offren sacrifices; and thei schulen not saue hem in the tyme of her turment.
13 Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
For thou, Juda, thi goddis weren bi the noumbre of thi citees, and thou settidist auters of schenschipe, bi the noumbre of the weies of Jerusalem, auters to offre sacrifices to Baalym.
14 “Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
Therfor nyle thou preie for this puple, and take thou not heriyng and preier for hem; for Y schal not here in the tyme of the cry of hem to me, in the tyme of the turment of hem.
15 “Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
What is it, that my derlyng doith many greet trespassis in myn hous? whether hooli fleischis schulen do awei fro thee thi malice, in which thou hast glorie?
16 Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
The Lord clepide thi name an olyue tre, fair, ful of fruyt, schapli; at the vois of a greet speche fier brent an hiy ther ynne, and the buyschis therof ben brent.
17 Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
And the Lord of oostis that plauntide thee, spak yuel on thee, for the yuels of the hous of Israel, and of the hous of Juda, whiche thei diden to hem silf, and offriden to Baalym, to terre me to wraththe.
18 Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
Forsothe, Lord, thou schewidist to me, and Y knew; thou schewidist to me the studies of hem.
19 Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
And Y am as a mylde lomb, which is borun to slayn sacrifice; and Y knew not, that thei thouyten counsels on me, and seiden, Sende we a tre in to the brede of hym, and rase we hym awei fro the lond of lyueris, and his name be no more hadde in mynde.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
But thou, Lord of oostis, that demest iustli, and preuest reynes and hertis, se Y thi veniaunce of hem; for to thee Y schewide my cause.
21 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
Therfor the Lord seith these thingis to the men of Anathot, that seken thi lijf, and seien, Thou schalt not prophesie in the name of the Lord, and thou schalt not die in oure hondis.
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Therfor the Lord of oostis seith these thingis, Lo! Y schal visite on hem; the yonge men of hem schulen die bi swerd, the sones of hem and the douytris of hem schulen die for hungur;
23 Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”
and no relifs, ether children abidynge, schulen be of hem; for Y schal bringe ynne yuel on the men of Anathot, the yeer of the visitacioun of hem.

< Jeremiah 11 >