< Jeremiah 11 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
Jeremiah khaeah angzo Angraeng ih lok loe hae tiah oh;
2 “Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
hae lokmaihaih hae tahngai ah loe, Judah hoi Jerusalem ah kaom kaminawk khaeah,
3 Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
Israelnawk ih Angraeng Sithaw mah, a lokmaihaih pazui ai kami loe tahamsethaih tong tih,
4 Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
Izip prae ih sum pakawhaih hmaipalai thung hoiah ka zaeh na niah, nam panawk khaeah:
5 Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
Ka lok hae tahngai oh, ka thuih ih lok baktiah sah oh, to tiah nahaeloe kai ih kami ah na om o ueloe, kai doeh nangcae ih Sithaw ah ka om tih. Vaihniah na toep o ih, tahnutui hoi khoitui longhaih prae to paek hanah, nam panawk khaeah lokkamhaih to ka koepsak han, tiah a thuih tiah, thui pae han ang naa. To naah kai mah, Aw Angraeng, to tiah om nasoe, tiah ka naa.
6 Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
Angraeng mah kai khaeah, Hae loknawk hae Judah vangpuinawk hoi Jerusalem ah kaom loklamnawk boih ah, Hae lokmaihaih loknawk hae tahngai oh loe, pazui oh, tiah thui ah, tiah ang naa.
7 Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
Izip prae hoiah nam panawk ka zaehhoihaih ni hoi kamtong vaihni ni khoek to, khawnthaw ah kang thawk moe, Ka lok hae tahngai oh, tiah acoehaih lok to ka thuih pae.
8 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
Toe nihcae mah tahngai o ai, naa doeh patueng o ai; angmacae kasae poekhaih palung mah thuih ih lok baktiah a caeh o lat; to pongah pazui hanah nihcae khaeah ka paek e, nihcae mah pazui o ai ih hae lokmaihaih loknawk boih nihcae nuiah ka kraksak han, tiah a thuih.
9 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
To pacoengah Angraeng mah, kai khaeah, Judah hoi Jerusalem ah kaom kaminawk salakah kasae sak pacaenghaih to oh.
10 Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
Kai ih loknawk tahngai koeh ai kaminawk loe, ampanawk sakpazaehaih bangah angqoi o boih let boeh; kalah sithawnawk ih toksak hanah hnukah bang o; Israel imthung takoh hoi Judah imthung takoh mah nihcae ampanawk hoiah ka sak ih lokmaihaih to phraek o boeh, tiah thuih.
11 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
To pongah Angraeng mah hae tiah thuih; Khenah, nihcae nuiah amrohaih ka phaksak han, nihcae loe loih o thai mak ai; nihcae mah kai khaeah hang o cadoeh, nihcae ih lok to ka tahngai pae mak ai.
12 Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
Judah vangpuinawk hoi Jerusalem ih kaminawk loe caeh o ueloe, hmuihoih thlaek o ih sithawnawk khaeah hang o tih; toe nihcae raihaih tong naah pahlong thai mak ai.
13 Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
Aw Judah, nangcae ih sithaw loe nangmacae ih vangpuinawk zetto pop o; Jerusalem ih lampuinawk zetto kaom Baal sithawnawk khaeah hmuihoih thlaek hanah, azat thok hmuen ah kaom, hmaicamnawk to na sak.
14 “Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
Jeremiah, to kaminawk hanah lawkthui pae hmah loe, tahmen hnikhaih hoiah doeh ban payangh pae hmah, raihaih tongh o moe, kai na kawk o cadoeh ka tahngai pae mak ai.
15 “Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
Ka palung ih kami loe pop parai kaminawk hoiah zaehaih sak pongah, anih loe ka im thungah timaw sah tih? Moi tathlanghaih mah nang danpaekhaih to loisak tih maw? Kahoih ai hmuen na sak naah mataeng doeh, poek kanawm ah na oh thaih.
16 Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
Angraeng mah, Kranghoih, athaih kahoih, kahing olive thing, tiah na hmin to kawk; toe na tanghangnawk loe katuen parai ah angkhaeh moe, hmai thlaek hanah kami to ka patoeh boeh.
17 Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
Israel imthung takoh hoi Judah imthung takoh loe Baal khaeah hmuihoih to thlaek o moe, kai palungphuisak hanah angmacae sethaih to a sak o pongah, nang kathling kami, misatuh Angraeng mah na nuiah amrohaih phaksak hanah lok takroek boeh.
18 Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
Angraeng mah panoek thaihaih ang paek pongah, ka panoek; to naah nihcae mah sak o ih hmuennawk to ang patuek.
19 Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
Kai loe hum han suek ih tuinom kahoih tuucaa baktiah ka oh; nihcae mah anih ih ahmin anghmatsak hanah, akung hoi athaih nawnto pakhruh o si loe, kahing kaminawk ih prae thung hoiah tamit si, tiah kai hum hanah pacaeng o ih hmuen to ka panoek ai.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
Toe, kaimah hae nang khaeah kang tathlang boeh, katoengah lokcaekkung, poekhaih palungthin khenkung, Aw misatuh kaminawk ih Angraeng, nihcae nuiah lu na lakhaih to na hnusak ah;
21 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
to pacoengah Angraeng Sithaw mah hae tiah thuih: Jeremiah, na hinghaih pakrong, Anathoth kaminawk mah, Kaicae ban hoi na duek han ai ah, Angraeng ih ahmin to thui hmah lai ah, tiah thuih o:
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
to pongah misatuh kaminawk ih Angraeng mah hae tiah thuih; Khenah, nihcae to ka thuitaek han; thendoengnawk loe sumsen hoiah dueh o tih; nihcae ih capa hoi canunawk doeh khokhahaih hoiah dueh o tih:
23 Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”
Maeto doeh anghmat o mak ai; nihcae thuitaekhaih saning ah, Anathoth kaminawk nuiah amrohaih ka phaksak han, tiah a thuih.

< Jeremiah 11 >