< Jeremiah 10 >

1 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
ای بنی‌اسرائیل، به پیامی که خداوند به شما می‌دهد، گوش فرا دهید:
2 Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
«از راه و رسم سایر قومها پیروی نکنید و مانند آنها از حرکات ستارگان و افلاک نترسید و فکر نکنید سرنوشت شما را آنها تعیین می‌کنند.
3 Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
رسوم آنها چقدر پوچ و احمقانه است؛ درختی از جنگل می‌برند و نجار با ابزارش از آن بُتی می‌سازد،
4 Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
سپس با طلا و نقره زینتش می‌دهند و با میخ و چکش آن را در محل استقرارش محکم می‌کنند تا نیفتد.
5 Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
درست مانند مترسکی در جالیز است که نه حرف می‌زند و نه راه می‌رود، بلکه کسی باید آن را بردارد و جابه‌جا نماید، پس شما از چنین بُتی نترسید! چون نه می‌تواند صدمه‌ای بزند و نه کمکی بکند.»
6 Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
ای خداوند، خدایی مثل تو وجود ندارد، چون تو بزرگی و نامت پرقدرت است!
7 Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
ای پادشاهِ تمام قومها، کیست که از تو نترسد؟ فقط تو شایستهٔ احترامی! در تمام سرزمینها و در بین تمام حکیمان، همتای تو یافت نمی‌شود!
8 Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
آنانی که بت می‌پرستند، همگی احمق و نادانند! از بتهای چوبی چه می‌توانند بیاموزند؟
9 Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
از سرزمین ترشیش ورقهای کوبیده شدهٔ نقره، و از «اوفاز» طلا می‌آورند و هنرمندان و زرگران ماهر، آنها را به روی بتها می‌کشند؛ سپس دوزندگان هنرمند از پارچه‌های آبی و ارغوانی، لباسهای زیبا می‌دوزند و بر آنها می‌پوشانند.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
ولی خداوندا، تو تنها خدای حقیقی می‌باشی، تو خدای زنده و پادشاه ابدی هستی! از خشم تو تمام زمین می‌لرزد، و قومها به هنگام غضب تو می‌گریزند و خود را پنهان می‌سازند!
11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
به کسانی که بت می‌پرستند بگویید: «خدایانی که در خلقت آسمان و زمین نقشی نداشته‌اند از روی زمین محو و نابود خواهند شد.»
12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
اما خدای ما با قدرت خود زمین را ساخت، و با حکمتش جهان را بنیاد نهاد و با دانایی خود آسمانها را به وجود آورد.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
به فرمان اوست که ابرها در آسمان می‌غرند؛ اوست که ابرها را از نقاط دور دست زمین برمی‌آورد، رعد و برق ایجاد می‌کند، باران می‌فرستد، و باد را از خزانه‌های خود بیرون می‌آورد!
14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
آنانی که در مقابل بتهایشان سجده می‌کنند چقدر نادانند! سازندگان آنها شرمسار و رسوا خواهند شد، زیرا آنچه می‌سازند، دروغین است و جان در آنها نیست.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
همهٔ این بتها بی‌ارزش و مسخره‌اند! وقتی سازندگانشان از بین بروند، بتهایشان هم از میان خواهند رفت.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
اما خدای یعقوب مثل این بتها نیست، او خالق همۀ موجودات است و بنی‌اسرائیل قوم خاص او می‌باشد؛ نام او خداوند لشکرهای آسمان است.
17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
ای شما که در محاصره به سر می‌برید، اموال خود را جمع کنید و آمادهٔ حرکت شوید!
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
زیرا خداوند می‌فرماید: «این بار شما را از این سرزمین بیرون خواهم انداخت و چنان بلایی بر سر شما نازل خواهم نمود که حتی یک نفرتان نیز جان به در نبرید!»
19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
در آن روزها مردم یهودا فریاد کرده، خواهند گفت: «زخمهایمان چقدر عمیق است! امیدی به شفا نیست! ولی باید تحمل کنیم چون این مجازات ماست!
20 Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
خانه و کاشانه‌مان خراب شده؛ بچه‌هایمان را از آغوشمان برده‌اند و دیگر هرگز آنها را نخواهیم دید؛ کسی هم باقی نمانده که به کمک او دوباره خانه‌مان را بسازیم».
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
شبانان و رهبران قوم اسرائیل احمق و نادان شده‌اند و دیگر از خداوند هدایت نمی‌طلبند؛ از این رو شکست خواهند خورد و قومشان مانند گله بی‌سرپرست پراکنده خواهند شد.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
اینک هیاهویی به گوش می‌رسد! هیاهوی لشکر بزرگی که از سوی شمال می‌آید تا شهرهای یهودا را ویران کند و آنها را لانهٔ شغالها سازد!
23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
ای خداوند، می‌دانم که انسان حاکم بر سرنوشت خود نیست و این توانایی را ندارد که مسیر زندگی خود را تعیین کند.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
خداوندا، ما را اصلاح کن، ولی با ملایمت، نه با خشم و غضب، و گرنه نابود می‌شویم.
25 Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.
آتش خشم و غضب خود را بر قومهایی بریز که تو را نمی‌شناسند و از تو پیروی نمی‌کنند، چون بنی‌اسرائیل را آنها از بین برده‌اند و این سرزمین را به کلی ویران کرده‌اند.

< Jeremiah 10 >