< Jeremiah 10 >

1 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
Ta thikĩrĩriai mũigue ũhoro ũrĩa Jehova ekũmwĩra, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli.
2 Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Tigai kwĩruta mĩthiĩre ya ndũrĩrĩ, kana mũguoyohio nĩ morirũ ma kũũrĩa igũrũ, o na gũtuĩka ndũrĩrĩ icio nĩiguoyohetio nĩmo.
3 Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
Nĩgũkorwo mĩtugo ya andũ acio ndĩrĩ kĩene: matemaga mũtĩ mũtitũ, ũkarutĩrwo wĩra nĩ bundi, akawacũhia na ithanwa rĩake.
4 Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
Maũgemagia na betha na thahabu; maũhũũragĩrĩra na mĩcumarĩ na nyondo ndũkae kwenyenya.
5 Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
Ũtariĩ ta kĩndũ gĩa kũhahũra nyamũ gĩthecereirwo mũtĩ mũgũnda-inĩ wa marenge, mĩhianano yao ndĩngĩhota kwaria; ningĩ no nginya ĩkuuo, tondũ ndĩngĩhota gwĩtwara. Mũtikanamĩĩtigĩre; ndĩngĩhota gwĩka ũũru o na kana gwĩka wega o na ũrĩkũ.”
6 Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Atĩrĩrĩ, gũtirĩ ũngĩ ũtariĩ tawe, Wee Jehova; Wee ũrĩ mũnene, narĩo rĩĩtwa rĩaku nĩ rĩrĩ ũhoti mũnene.
7 Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
Nũũ ũtangĩgwĩtigĩra, Wee mũthamaki wa ndũrĩrĩ? Wee nowe wagĩrĩire gwĩtigĩrwo. Thĩinĩ wa andũ arĩa othe oogĩ a ndũrĩrĩ, o na mothamaki-inĩ mao mothe, gũtirĩ ũngĩ ũhaana tawe.
8 Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
Acio othe-rĩ, matiĩciiragia, no nĩ akĩĩgu; mataaragwo nĩ mĩhianano ĩtarĩ kĩene o ĩrĩa ĩthondeketwo na mĩtĩ.
9 Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
Ĩgemagio na betha ĩrĩa hũũre ĩrutĩtwo Tarishishi, na thahabu ĩrutĩtwo Ufazu. Kĩndũ kĩu gĩthondeketwo na moko ma bundi, na ma mũturi wa thahabu gĩcookaga gĩkahumbĩrwo na rangi wa bururu na wa ndathi, ciothe ithondeketwo nĩ andũ arĩa oogĩ na wĩra ũcio.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
No Jehova nĩwe Ngai ũrĩa wa ma; nĩwe Ngai ũrĩa ũrĩ muoyo, o na mũthamaki ũrĩa ũtũũraga tene na tene. Rĩrĩa arakarĩte-rĩ, thĩ nĩĩthingithaga, nacio ndũrĩrĩ itingĩĩtiiria mangʼũrĩ make.
11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
“Meerei atĩrĩ, ‘Ngai icio itoombire igũrũ na thĩ, nĩigathira gũkũ thĩ, na ithire kũrĩa guothe gũtambũrũkĩirio matu mairũ.’”
12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
No rĩrĩ, nĩ Ngai wombire thĩ na hinya wake; akĩhaanda thĩ na ũũgĩ wake, na agĩtambũrũkia matu mairũ na ũndũ wa ũmenyo wake.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Hĩndĩ ĩrĩa we agũũthũka-rĩ, maaĩ marĩa marĩ igũrũ matu-inĩ nĩmarurumaga; nĩwe ũtũmaga thaatũ waambate na igũrũ uumĩte ituri ciothe cia thĩ. Atũmaga rũheni rũũke rũrehanĩte na mbura, na akarehithia rũhuho ruumĩte makũmbĩ-inĩ make.
14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
Andũ othe nĩmagĩte meciiria na makaaga ũũgĩ; nake mũturi wa thahabu o wothe nĩaconorithĩtio nĩ mĩhianano ĩyo yake. Nĩ ũndũ mĩhianano ĩyo yake ya gwĩturĩra nĩ ya maheeni; ndĩrĩ mĩhũmũ thĩinĩ wayo.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
Ndĩrĩ kĩene, nĩ ya kũnyararwo; narĩo ihinda rĩayo rĩa gũciirithio rĩakinya-rĩ, nĩĩgathira biũ.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
We ũcio Rũgai rwa Jakubu ndatariĩ tayo, nĩgũkorwo nĩwe Mũũmbi wa indo ciothe, o hamwe na Isiraeli mũhĩrĩga ũrĩa, eegwatĩire ũtuĩke igai rĩake, Jehova Mwene-Hinya-Wothe, nĩrĩo rĩĩtwa rĩake.
17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
Ohai mĩrigo yanyu mũthaame bũrũri ũyũ, inyuĩ arĩa mũtũũrĩte mũrigiicĩirio nĩ thũ.
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
Nĩgũkorwo Jehova ekuuga atĩrĩ: “Ihinda rĩĩrĩ nĩrĩo ngũikia andũ arĩa othe matũũraga bũrũri ũyũ ta maikĩtio na kĩgũtha; Nĩngũmarehithĩria mĩnyamaro, nĩgeetha manyiitwo mĩgwate.”
19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
Wũi-ĩiya-wakwa, nĩ ũndũ wa itihia rĩrĩa ndiihĩtio-ĩ! Ironda ciakwa itingĩhona! No ngĩĩcookeria ũhoro ngiuga atĩrĩ, “Ũyũ nĩ mũrimũ wakwa, na no nginya ndĩũkirĩrĩrie.”
20 Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
Hema yakwa nĩyanangĩtwo, nayo mĩkanda yayo yothe ĩgatuĩkanga. Ariũ akwa nĩmanjehereire magethiĩra na rĩu matikĩrĩ ho; rĩu gũtirĩ mũndũ mũtigaru wa kwamba hema yakwa, o na kana wa gũtambũrũkia mataama mayo.
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
Arĩithi matiĩciiragia, na matituĩragia ũhoro harĩ Jehova; nĩ ũndũ ũcio matigaacagĩra, nacio ndũũru ciao ciothe cia mbũri nĩihurunjũkĩte.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
Ta thikĩrĩriai! Nĩtũrakinyĩrio ũhoro, tũkeerwo atĩrĩ, kũrĩ na gacagaca nene kuuma bũrũri wa mwena wa gathigathini! Gacagaca ĩyo nĩĩgatũma matũũra ma Juda makire ihooru, ĩtũme matuĩke ma gũtũũragwo nĩ mbwe.
23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
Atĩrĩrĩ Wee Jehova, nĩnjũũĩ atĩ muoyo wa mũndũ ti wake we mwene; mũndũ we mwene ti we ũrũngagĩrĩria makinya make.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
Atĩrĩrĩ Wee Jehova, herithia, no ũherithie na kĩhooto; ndũkaherithie ũrĩ na marakara, ndũkae kũniina nduĩke kĩndũ hatarĩ.
25 Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.
Itũrũrĩra ndũrĩrĩ iria itakũũĩ mangʼũrĩ maku, ũmaitũrũrĩre andũ arĩa matakayagĩra rĩĩtwa rĩaku. Nĩ ũndũ-rĩ, nĩmahukĩtie Jakubu; mamũhukĩtie biũ, naguo bũrũri wake makawananga.

< Jeremiah 10 >