< Jeremiah 10 >

1 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
Écoutez la parole que l'Éternel vous adresse, maison d'Israël!
2 Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
Yahvé dit, « N'apprenez pas la voie des nations, et ne soyez pas consternés par les signes du ciel; car les nations sont consternées par eux.
3 Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
Car les coutumes des peuples ne sont que vanité; car on coupe un arbre de la forêt, le travail des mains de l'ouvrier à la hache.
4 Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
Ils le décorent d'argent et d'or. Ils le fixent avec des clous et avec des marteaux, pour qu'il ne puisse pas bouger.
5 Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
Ils sont comme un palmier, dont le travail est tourné, et ne parle pas. Ils doivent être portés, parce qu'ils ne peuvent pas bouger. N'ayez pas peur d'eux; car ils ne peuvent pas faire le mal, il n'est pas en eux de faire le bien. »
6 Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Il n'y a personne comme toi, Yahvé. Tu es génial, et ton nom est grand en puissance.
7 Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
qui ne devraient pas vous craindre, Roi des nations? Car il vous appartient. Parce que parmi tous les sages des nations, et dans tout leur domaine royal, il n'y a personne comme toi.
8 Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
Mais ils sont tous ensemble brutaux et stupides, instruits par les idoles! C'est juste du bois.
9 Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
Il y a de l'argent battu en plaques, qu'on apporte de Tarsis, et l'or d'Uphaz, le travail du graveur et des mains de l'orfèvre. Leurs vêtements sont bleus et violets. Ils sont tous l'œuvre d'hommes habiles.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
Mais Yahvé est le vrai Dieu. Il est le Dieu vivant, et un Roi éternel. A sa colère, la terre tremble. Les nations ne sont pas capables de résister à son indignation.
11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
« Tu leur diras ceci: « Les dieux qui n'ont pas fait les cieux et la terre disparaîtront de la terre et de sous les cieux. »
12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
Dieu a fait la terre par sa puissance. Il a établi le monde par sa sagesse, et c'est par son intelligence qu'il a déployé les cieux.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Quand il fait entendre sa voix, les eaux dans les cieux rugissent, et il fait monter les vapeurs des extrémités de la terre. Il fait des éclairs pour la pluie, et fait sortir le vent de ses trésors.
14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
Tout homme est devenu brutal et sans connaissance. Tout orfèvre est déçu par son image gravée; car son image en fusion n'est que mensonge, et il n'y a pas de souffle en eux.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
Ils sont une vanité, une œuvre d'égarement. Au moment de leur visite, ils périront.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
La part de Jacob n'est pas comme celles-ci; car il est le créateur de toutes choses; et Israël est la tribu de son héritage. Yahvé des Armées est son nom.
17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
Rassemblez vos marchandises dans le pays, vous qui vivez en état de siège.
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
Car Yahvé dit, « Voici qu'en ce moment, je vais frapper les habitants du pays, et les affligera, afin qu'ils le ressentent. »
19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
Malheur à moi, à cause de ma blessure! Ma blessure est grave; mais j'ai dit, « En vérité, c'est mon chagrin, et je dois le supporter. »
20 Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
Ma tente a été détruite, et tous mes liens sont rompus. Mes enfants se sont éloignés de moi, et ils ne sont plus. Il n'y a plus personne pour étendre ma tente, pour installer mes rideaux.
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
Car les bergers sont devenus brutaux, et n'ont pas demandé l'avis de Yahvé. C'est pourquoi ils n'ont pas prospéré, et tous leurs troupeaux se sont dispersés.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
La voix de la nouvelle, la voici, elle vient, et une grande agitation venant du pays du nord, pour faire des villes de Juda une désolation, un lieu de résidence pour les chacals.
23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
Yahvé, je sais que la voie de l'homme n'est pas en lui-même. Il n'appartient pas à l'homme qui marche de diriger ses pas.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
Yahvé, corrige-moi, mais doucement; pas dans votre colère, de peur que tu ne me réduises à néant.
25 Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.
Répands ta colère sur les nations qui ne te connaissent pas, et sur les familles qui n'invoquent pas ton nom; car ils ont dévoré Jacob. Oui, ils l'ont dévoré, consumé, et ont détruit sa maison.

< Jeremiah 10 >