< Jeremiah 10 >
1 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
You people of Israel, listen to what Yahweh says:
2 Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
“Do not act like the people of [other] nations act, and do not be terrified by strange/unusual things that you see in the sky, even though they cause the [people of other] nations to be terrified.
3 Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
The customs of the people [of other nations] are worthless. [For example], they cut down a tree in the forest. Then a [skilled] worker/craftsman [cuts a section of it and] uses his chisel to carve an idol from that section.
4 Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
[Then] people decorate the idol with silver and gold. [Then] they fasten it securely with nails in order that it will not topple/fall over.
5 Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
[Then] the idol [stands there] like [SIM] a scarecrow in a field of cucumbers/melons! It cannot speak, and people must carry it, because it cannot walk. Do not be afraid of idols, because they cannot harm [anyone], and they cannot do [anything] good [to help anyone].”
6 Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Yahweh, there is no one like you. You [MTY] are great, and you are very powerful.
7 Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
You are the king of all the nations! Everyone should [RHQ] revere you, because that is what you deserve. Among all the wise people on the earth and in all the kingdoms where they live, (there is no one like you./who can compare with you?)
8 Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
Those people who [think that they are] very wise [IRO] are stupid and foolish [DOU]. The idols that they worship are only made of wood! Those idols certainly cannot teach them anything.
9 Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
People hammer into thin sheets silver from Tarshish and gold from Uphaz, and then they give those sheets of silver and gold to skilled workers/craftsmen to cover the idols. Then they put on those idols expensive purple robes that are made by skilled workers.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
But Yahweh is the [only] true God; he is the all-powerful God, the king [who rules] forever. When he is angry, [all] the earth shakes/quakes; and [the people of] the nations cannot endure [what he does] when he is angry [with them].
11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
[You Israeli people], tell this to those people: “Those idols did not make the sky and the earth, and they will disappear from the earth.”
12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
But [Yahweh] made the earth by his power; he established it [firmly] by his wisdom and stretched out the sky by his understanding.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
When he speaks [loudly], there is thunder in the sky; he causes clouds to form over every part of the earth. He sends lightning with the rain and releases the winds from his storehouses.
14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
People are senseless and know very little [HYP]; those who make idols are always disappointed because their idols do nothing for them. The images/statues that they make are not real [gods]; they are lifeless.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
Idols are worthless; they deserve to be ridiculed; there will be a time when they [all] will be destroyed.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
But the God whom we Israelis worship is not like those idols; he is the one who created everything [that exists]; we, the tribe/people of Israel, belong to him; he is the Commander of the armies of angels.
17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
[Yahweh says this to the people of Jerusalem]: “The army of your enemies surrounds your city, so gather up your possessions [and prepare] to leave the city.
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
I will soon throw you out of this land and cause you to experience great troubles, with the result that you will have severe pain (OR, none of you will be left here).”
19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
[The people replied, “It is as though] we have been [badly] wounded, and we are very grieved; [It is as though] we have a very serious illness, and we must endure the pain.
20 Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
[It is as though] our [great] tent is destroyed; the ropes [that held it up] have been cut; our children have gone away from us and will not return; there are no people left to rebuild our great tent.
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
Our leaders [MET] no [longer] have any sense; they no [longer] ask Yahweh [to (guide them/tell them what to do)], so they will no [longer] prosper, and all those over whom they rule [MET] will be scattered.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
Listen! [Our enemies’ armies] in the north are making a [very] big noise/commotion [as they march toward us]. The towns in Judah will be destroyed, [and they will become] a place where jackals/wolves live.”
23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
Yahweh, I know that no person controls what will happen to him; no one is able to direct the events that he will experience.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
[So] correct/discipline us, but do it gently. Do not correct/punish us when you are angry, because we would die if you did that.
25 Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.
Punish [MTY] [all] the nations whose people do not acknowledge/say that you are God; punish all the nations whose people do not worship you, because they are completely destroying [DOU] [us people of] Israel and they are causing our land to soon be only a desert.