< Jeremiah 1 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
Słowa Jeremiasza, syna Chilkiasza, z [rodu] kapłanów, którzy [byli] w Anatot, w ziemi Beniamina;
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
Do którego doszło słowo PANA za dni Jozjasza, syna Amona, króla Judy, w trzynastym roku jego panowania.
3 àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
Doszło także za dni Joakima, syna Jozjasza, króla Judy, aż do końca jedenastego roku Sedekiasza, syna Jozjasza, króla Judy, aż do uprowadzenia do niewoli [mieszkańców] Jerozolimy w piątym miesiącu;
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
Doszło do mnie słowo PANA mówiące:
5 “Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
Zanim ukształtowałem cię w łonie, znałem cię, zanim wyszedłeś z łona, uświęciłem cię i ustanowiłem prorokiem dla narodów.
6 Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
Wtedy powiedziałem: Ach, Panie BOŻE! Oto nie umiem mówić, bo jestem dzieckiem.
7 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
Ale PAN powiedział do mnie: Nie mów: Jestem dzieckiem. Pójdziesz bowiem, do kogokolwiek cię poślę, i będziesz mówił, cokolwiek ci rozkażę.
8 Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
Nie bój się ich twarzy, bo ja [jestem] z tobą, aby cię wybawić, mówi PAN.
9 Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
Wtedy PAN wyciągnął swoją rękę i dotknął moich ust. I powiedział do mnie PAN: Oto wkładam moje słowa do twoich ust.
10 Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
Patrz, dziś ustanawiam cię nad narodami i królestwami, abyś wykorzeniał, burzył, wytracał i niszczył, byś budował i sadził.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
Potem doszło do mnie słowo PANA mówiące: Co widzisz, Jeremiaszu? I odpowiedziałem: Widzę gałązkę migdałowca.
12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
I PAN powiedział do mnie: Dobrze widzisz. Ja bowiem przyspieszam swoje słowo, aby je wykonać.
13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
Ponownie doszło do mnie słowo PANA mówiące: Co widzisz? Odpowiedziałem: Widzę wrzący kocioł, a jego przednia strona [skierowana jest] ku północy.
14 Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
I PAN powiedział do mnie: Od północy spadnie nieszczęście na wszystkich mieszkańców tej ziemi;
15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
Bo oto zwołam wszystkie rody z królestw północnych, mówi PAN, i przyjdą, a każdy z nich ustawi swój tron u wejścia do bram Jerozolimy, przeciw wszystkim jej murom i przeciw miastom Judy.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
I ogłoszę przeciwko nim moje sądy za całą ich niegodziwość: [przeciwko] tym, którzy mnie opuścili, palili kadzidło innym bogom i oddali pokłon dziełom swoich rąk.
17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
Dlatego ty przepasz swoje biodra, wstań i mów do nich wszystko, co ci nakazuję. Nie bój się ich twarzy, bym cię nie napełnił lękiem przed nimi.
18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Oto bowiem ustanawiam cię dziś miastem obronnym, żelazną kolumną i murem spiżowym przeciwko całej tej ziemi, przeciwko królom Judy, ich książętom, ich kapłanom i ludowi tej ziemi.
19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.
I będą walczyć przeciwko tobie, ale cię nie przemogą, bo ja jestem z tobą, mówi PAN, aby cię wybawić.

< Jeremiah 1 >