< Jeremiah 1 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
Słowa Jeremijasza, syna Helkijaszowego, z kapłanów, którzy byli w Anatot, w ziemi Benjamin
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
Do którego stało się słowo Pańskie za dni Jozyjasza, syna Amonowego, króla Judzkiego trzynastego roku królowania jego.
3 àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
A stało się za dni Joakima, syna Jozyjaszowego, króla Judzkiego, aż do skończenia jedenastego roku Sedekijasza, syna Jozyjasza, króla Judzkiego, aż do przeprowadzenia Jeruzalemczyków, miesiąca piątego,
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
Stało się mówię, słowo Pańskie do mnie, mówiąc
5 “Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
Pierwej niżelim cię utworzył w żywocie, znałem cię, a pierwej niżeliś wyszedł z żywota, poświęciłem cię, za proroka narodom dałem cię.
6 Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
I rzekłem: Ach, ach panujący Panie! Oto nie umiem mówić, bom jest dziecięciem.
7 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
Ale Pan rzekł do mnie: Nie mów: Jestem dziecięciem, owszem, na wszystko, na co cię poślę, idź, a wszystko, coć rozkażę, mów
8 Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
Nie bój się oblicza ich, bom Ja jest z tobą, abym cię wybawił, mówi Pan.
9 Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
A wyciągnąwszy Pan rękę swoję, dotknął się ust moich, i rzekł mi Pan: Otom dał słowa moje do ust twoich.
10 Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
Oto cię dziś postanawiam nad narodami i nad królestwami, abyś wykorzeniał, i psuł, i wytracał, i obalał, i abyś budował i szczepił.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
Potem stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc: Co widzisz Jeremijaszu? I rzekłem: Widzę rózgę migdałową.
12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
I rzekł Pan do mnie: Dobrze widzisz: albowiem się Ja pospieszam z słowem swem, abym je wykonał.
13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
I stało się słowo Pańskie do mnie powtóre, mówiąc: Co widzisz? I rzekłem: Widzę garniec wrzący, a przednia strona jego ku stronie północnej.
14 Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
I rzekł Pan do mnie: Od północy przypadnie złe na wszystkich mieszkających na tej ziemi.
15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
Bo oto Ja zawołam wszystkich rodzajów z królestw północnych, mówi Pan, aby przyciągnąwszy każdy z nich, postanowił stolicę swoję w wejściu bram Jeruzalemskich i przy wszystkich murach jego, i przy wszystkich miastach Judzkich.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
A tak opowiem sądy moje przeciwko nim dla wszelakiej złości tych, którzy mię opuścili, a kadzili bogom obcym, i kłaniali się robocie rąk swoich.
17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
Przetoż ty przepasz biodra swoje, a wstawszy mów do nich wszystko, co Ja tobie rozkazuję, nie bój się ich bym cię snać nie starł przed obliczem ich,
18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Bo oto Ja postanawiam cię dziś miastem obronnem, i słupem żelaznym, i murem miedzianym przeciwko tej wszystkiej ziemi, przeciwko królom Judzkim, przeciwko książętom ich, przeciwko kapłanom ich, i przeciwko ludowi tej ziemi;
19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.
Którzy walczyć będą przeciwko tobie, ale cię nie przemogą: bom Ja z tobą mówi Pan, abym cię wybawił.

< Jeremiah 1 >