< Jeremiah 1 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
Jeremijas vārdi, kas bija Hilķijas dēls, no tiem priesteriem Anatotā Benjamina zemē.
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
Uz to Tā Kunga vārds notika Josijas, Amona dēla, Jūda ķēniņa dienās, viņa valdīšanas trīspadsmitā gadā.
3 àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
Tāpat uz viņu notika Jojaķima, Josijas dēla, Jūda ķēniņa dienās, kamēr beidzās Cedeķijas, Josijas dēla, Jūda ķēniņa, vienpadsmitais gads, kad Jeruzālemes ļaudis tapa aizvesti piektā mēnesī.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
Un Tā Kunga vārds notika uz mani un sacīja:
5 “Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
Pirms Es tevi radīju mātes miesās, Es tevi esmu pazinis, un pirms tu iznāci no mātes miesām, Es tevi esmu svētījis; tautām par pravieti Es tevi esmu licis.
6 Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
Tad es sacīju: ak Kungs, Dievs, redzi, es neprotu runāt, jo es esmu jauns.
7 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
Bet Tas Kungs uz mani sacīja: nesaki, es esmu jauns; jo visur, kurp Es tevi sūtīšu, tev būs iet, un visu, ko Es tev pavēlēšu, tev būs runāt.
8 Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
Nebīsties no viņiem, jo Es esmu ar tevi un tevi izglābšu, saka Tas Kungs.
9 Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
Un Tas Kungs izstiepa Savu roku un aizskāra manu muti, un Tas Kungs sacīja uz mani: redzi, Es lieku Savus vārdus tavā mutē.
10 Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
Redzi, Es tevi šodien ieceļu pār tautām un pār valstīm, izraut un salauzīt un izdeldēt un izpostīt, tad uztaisīt un dēstīt.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
Un Tā Kunga vārds uz mani notika un sacīja: ko tu redzi, Jeremija? Un es sacīju: es redzu zizli (mandeļu koka zaru).
12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
Un Tas Kungs uz mani sacīja: tu esi labi redzējis; jo Es būšu nomodā par Savu vārdu, ka Es to daru.
13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
Un Tā Kunga vārds notika uz mani otru reiz un sacīja: ko tu redzi? Un es sacīju: es redzu verdošu podu no ziemeļa puses.
14 Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
Un Tas Kungs uz mani sacīja: no ziemeļa puses ļaunums gāzīsies pār visiem zemes iedzīvotājiem.
15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
Jo redzi, Es saucu visas ķēniņu valstu ciltis no ziemeļa puses, saka Tas Kungs, un tie nāks un cels ikviens savu krēslu priekš Jeruzālemes vārtu durvīm un pret visiem viņas mūriem visapkārt un pret visām Jūda pilsētām.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
Un Es spriedīšu Savu sodību pret viņiem par visu viņu ļaunumu, ka tie Mani atstājuši un kvēpinājuši citiem dieviem un klanījušies priekš savu roku darba.
17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
Tu tad apjoz savus gurnus un celies un runā uz tiem visu, ko Es tev pavēlēšu; neiztrūcinājies priekš viņiem, lai Es tevi neiztrūcināju viņu priekšā.
18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Jo redzi, Es tevi šodien ceļu par stipru pilsētu un par dzelzs stabu un par vara mūri pret visu šo zemi, pret Jūda ķēniņiem, pret viņu lielkungiem, pret viņu priesteriem un pret tās zemes ļaudīm.
19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.
Un tie karos pret tevi, bet nekā neiespēs pret tevi; jo Es esmu ar tevi, saka Tas Kungs, tevi izglābt.

< Jeremiah 1 >