< James 5 >

1 Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin ọlọ́rọ̀, ẹ máa sọkún kí ẹ sì máa pohùnréré ẹkún nítorí òsì tí ó ń bọ̀ wá ta yín.
Tehát ti gazdagok, sírjatok, és jajgassatok, a rátok következő nyomorúságaitok miatt.
2 Ọrọ̀ yín díbàjẹ́, kòkòrò sì ti jẹ aṣọ yín.
Gazdagságotok megrohadt, ruháitokat megette a moly.
3 Wúrà òun fàdákà yín díbàjẹ́; ìbàjẹ́ wọn ni yóò sì ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, tí yóò sì jẹ ẹran-ara yín bí iná. Ẹ̀yin tí kó ìṣúra jọ de ọjọ́ ìkẹyìn.
Aranyotokat és ezüstötöket rozsda fogta meg, és azok rozsdája ellenetek tanúskodik, és megemészti testeteket, mint a tűz. Kincset gyűjtöttetek még az utolsó napokban is.
4 Kíyèsi i, ọ̀yà àwọn alágbàṣe tí wọ́n ti ṣe ìkórè oko yín, èyí tí ẹ kò san, ń ké rara; àti igbe àwọn tí ó ṣe ìkórè sì ti wọ inú etí Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Íme, a ti mezőtöket learató munkások bére, amit visszatartottatok, az égre kiált. És az aratók kiáltásai eljutottak a Seregek Urának fülébe.
5 Ẹ̀yin ti jẹ adùn ní ayé, ẹ̀yin sì ti fi ara yín fún ayé jíjẹ; ẹ̀yin ti mú ara yín sanra de ọjọ́ pípa.
Dőzsöltetek e földön és tobzódtatok. Szíveteket hizlaltátok az áldozat bemutatásának napjára.
6 Ẹ̀yin ti dá ẹ̀bi fún olódodo, ẹ sì ti pa á; ẹni tí kò kọ ojú ìjà sí yín.
Elítéltétek, megöltétek az igazat, s ő nem állt ellen nektek.
7 Nítorí náà ará, ẹ mú sùúrù títí di ìpadà wá Olúwa. Kíyèsi i, àgbẹ̀ a máa retí èso iyebíye ti ilẹ̀, a sì mú sùúrù dè é, títí di ìgbà àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò.
Legyetek azért, atyámfiai, béketűrők az Úrnak eljöveteléig. Íme a szántóvető várja a földnek drága gyümölcsét. Béketűréssel várja, míg reggeli és esti esőt kap.
8 Ẹ̀yin pẹ̀lú, ẹ mú sùúrù; ẹ fi ọkàn yín balẹ̀, nítorí ìpadà wá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
Legyetek ti is béketűrők, és erősítsétek meg szíveteket, mert az Úr eljövetele közel van.
9 Ẹ má ṣe kùn sí ọmọnìkejì yín, ará, kí a má ba à dá a yín lẹ́bi: kíyèsi i, onídàájọ́ dúró ní ẹnu ìlẹ̀kùn.
Ne panaszkodjatok egymásra, testvéreim, hogy el ne ítéltessetek! Íme a bíró az ajtó előtt áll.
10 Ará mi, ẹ fi àwọn wòlíì tí ó ti ń sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa ṣe àpẹẹrẹ ìyà jíjẹ, àti sùúrù.
Vegyetek példát, atyámfiai, szenvedésben és tűrésben a prófétáktól, akik az Úr nevében szóltak.
11 Sá à wò ó, àwa a máa ka àwọn tí ó fi ara dà ìyà sí ẹni ìbùkún. Ẹ̀yin ti gbọ́ ti sùúrù Jobu, ẹ̀yin sì rí ìgbẹ̀yìn tí Olúwa ṣe; pé Olúwa kún fún ìyọ́nú, ó sì ní àánú.
Íme boldognak mondjuk a tűrni tudókat. Jób tűréséről hallottatok, és láttátok, hogyan intézte az Úr a sorsát. Mert igen irgalmas és könyörületes az Úr.
12 Ṣùgbọ́n ju ohun gbogbo lọ, ará mi, ẹ má ṣe ìbúra, ìbá à ṣe fífi ọ̀run búra, tàbí ilẹ̀, tàbí ìbúra-kíbúra mìíràn. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí “Bẹ́ẹ̀ ni” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni; àti “Bẹ́ẹ̀ kọ́” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ kọ́; kí ẹ má ba à bọ́ sínú ẹ̀bi.
Mindenekelőtt pedig ne esküdjetek, atyámfiai, se az égre, se a földre, se semmi más egyébre. Hanem legyen a ti igenetek igen, és a nem nem, hogy ítélet alá ne essetek.
13 Inú ẹnikẹ́ni ha bàjẹ́ nínú yín bí? Jẹ́ kí ó gbàdúrà. Inú ẹnikẹ́ni ha dùn? Jẹ́ kí ó kọrin mímọ́.
Szenved-e valaki köztetek? Imádkozzék. Öröme van-e valakinek? Dicséretet énekeljen.
14 Ẹnikẹ́ni ha ṣe àìsàn nínú yín bí? Kí ó pe àwọn àgbà ìjọ, kí wọ́n sì gbàdúrà sórí rẹ̀, kí wọn fi òróró kùn ún ní orúkọ Olúwa.
Beteg-e valaki köztetek? Hívja magához a gyülekezet elöljáróit, és imádkozzanak érte, és kenjék meg olajjal az Úr nevében.
15 Àdúrà ìgbàgbọ́ yóò sì gba aláìsàn náà là, Olúwa yóò sì gbé e dìde; bí ó bá sì ṣe pé ó ti dẹ́ṣẹ̀, a ó dáríjì í.
És a hitből való imádság megtartja a beteget, és az Úr felsegíti őt. És ha bűnt követett is el, megbocsáttatik neki.
16 Ẹ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín fún ara yín, kí ẹ sì máa gbàdúrà fún ara yín, kí a lè mú yín láradá. Iṣẹ́ tí àdúrà olódodo ń ṣe ní agbára púpọ̀.
Valljátok meg bűneiteket egymásnak és imádkozzatok egymásért, hogy meggyógyuljatok, mert igen hasznos az igaznak buzgóságos könyörgése.
17 Ènìyàn bí àwa ni Elijah, ó gbàdúrà gidigidi pé kí òjò kí ó má ṣe rọ̀, òjò kò sì rọ̀ sórí ilẹ̀ fún ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà.
Illés ember volt, hozzánk hasonló és imádságban kérte, hogy ne legyen eső, és nem volt eső a földön három esztendeig és hat hónapig.
18 Ó sì tún gbàdúrà, ọ̀run sì tún rọ̀jò, ilẹ̀ sì so èso rẹ̀ jáde.
És ismét imádkozott és az ég esőt adott és a föld megteremte gyümölcsét.
19 Ará, bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ẹni kan sì yí i padà;
Atyámfiai, ha valaki közöttetek eltévelyedik az igazságtól, és megtéríti valaki,
20 jẹ́ kí ó mọ̀ pé, ẹni tí ó bá yí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan padà kúrò nínú ìṣìnà rẹ̀, yóò gba ọkàn kan là kúrò lọ́wọ́ ikú, yóò sì bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.
tudja meg, hogy aki megtérít egy bűnöst tévelygő útjáról, megmenti annak lelkét a haláltól, és sok bűnét elfedezi.

< James 5 >