< James 5 >
1 Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin ọlọ́rọ̀, ẹ máa sọkún kí ẹ sì máa pohùnréré ẹkún nítorí òsì tí ó ń bọ̀ wá ta yín.
ⲁ̅ⲀⲄⲈ ϮⲚⲞⲨ ⲚⲒⲢⲀⲘⲀⲞⲒ ⲢⲒⲘⲒ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲈⲦⲈⲚⲦⲀⲖⲈⲠⲰⲢⲒⲀ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ⲈϪⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ
2 Ọrọ̀ yín díbàjẹ́, kòkòrò sì ti jẹ aṣọ yín.
ⲃ̅ⲦⲈⲦⲈⲚⲘⲈⲦⲢⲀⲘⲀⲞ ⲀⲤⲦⲀⲔⲞ ⲚⲈⲦⲈⲚϨⲂⲰⲤ ⲀⲦϨⲞⲖⲒ ⲞⲨⲞⲘⲞⲨ
3 Wúrà òun fàdákà yín díbàjẹ́; ìbàjẹ́ wọn ni yóò sì ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, tí yóò sì jẹ ẹran-ara yín bí iná. Ẹ̀yin tí kó ìṣúra jọ de ọjọ́ ìkẹyìn.
ⲅ̅ⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲞⲨⲂ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲦⲈⲚϨⲀⲦ ⲀϤⲈⲢϢⲎ ⲒⲂⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲞⲨϢⲎⲒⲂⲒ ⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈⲨⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲞⲨⲞϨ ϤⲚⲀⲞⲨⲰⲘ ⲚⲤⲀⲚⲈⲦⲈⲚⲤⲀⲢⲜ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲞⲨⲬⲢⲰⲘ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲐⲰⲞⲨϮ ⲈϦⲞⲨⲚ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲈϨⲞⲞⲨ ⲚϦⲀⲈ.
4 Kíyèsi i, ọ̀yà àwọn alágbàṣe tí wọ́n ti ṣe ìkórè oko yín, èyí tí ẹ kò san, ń ké rara; àti igbe àwọn tí ó ṣe ìkórè sì ti wọ inú etí Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
ⲇ̅ϨⲎⲠⲠⲈ ⲒⲤ ⲪⲂⲈⲬⲈ ⲚⲦⲈⲚⲒⲈⲢⲄⲀⲦⲎⲤ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲰⲤϦ ⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲬⲰⲢⲀ ⲪⲎ ⲈⲦϤⲎϪ ⲚⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲤⲘⲎ ⲚⲦⲈⲚⲒϬⲀⲒⲰⲤϦ ⲀⲨϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲚⲈⲚⲘⲀϢϪ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲤⲀⲂⲀⲰⲐ
5 Ẹ̀yin ti jẹ adùn ní ayé, ẹ̀yin sì ti fi ara yín fún ayé jíjẹ; ẹ̀yin ti mú ara yín sanra de ọjọ́ pípa.
ⲉ̅ⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲚⲞϤ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲀⲚⲞⲚⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲀⲚϢ ⲚⲚⲈⲦⲈⲚϨⲎ ⲦⲈⲠⲈϨⲞⲞⲨ ⲘⲠϦⲞⲖϦⲈⲖ
6 Ẹ̀yin ti dá ẹ̀bi fún olódodo, ẹ sì ti pa á; ẹni tí kò kọ ojú ìjà sí yín.
ⲋ̅ⲀⲦⲈⲦⲈⲚϮϨⲀⲠ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϦⲰⲦⲈⲂ ⲘⲠⲒⲐⲘⲎⲒ ⲚϤϮ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϨⲢⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲀⲚ
7 Nítorí náà ará, ẹ mú sùúrù títí di ìpadà wá Olúwa. Kíyèsi i, àgbẹ̀ a máa retí èso iyebíye ti ilẹ̀, a sì mú sùúrù dè é, títí di ìgbà àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò.
ⲍ̅ⲰⲞⲨⲚϨⲎⲦ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ϢⲀ ⲦⲠⲀⲢⲞⲨⲤⲒⲀ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲒⲤ ⲠⲒⲞⲨⲰⲒ ⲈϤϪⲞⲨϢⲦ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲒⲞⲨⲦⲀϨ ⲈⲦⲦⲀⲒⲎⲞⲨⲦ ⲚⲦⲈⲠⲔⲀϨⲒ ⲞⲨⲞϨ ϤⲰⲞⲨⲚϨⲎⲦ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ ϢⲀⲦⲈϤϬⲒ ⲘⲠⲒϢⲞⲢⲠ ⲚⲞⲨⲦⲀϨ ⲚⲈⲘ ⲠⲒϦⲀⲈ
8 Ẹ̀yin pẹ̀lú, ẹ mú sùúrù; ẹ fi ọkàn yín balẹ̀, nítorí ìpadà wá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
ⲏ̅ⲰⲞⲨⲚϨⲎⲦ ϨⲰⲦⲈⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀⲦⲀϪⲢⲈ ⲚⲈⲦⲈⲚϨⲎⲦ ϪⲈ ⲀⲤϦⲰⲚⲦ ⲚϪⲈϮⲠⲀⲢⲞⲨⲤⲒⲀ ⲚⲦⲈⲠϬⲤ
9 Ẹ má ṣe kùn sí ọmọnìkejì yín, ará, kí a má ba à dá a yín lẹ́bi: kíyèsi i, onídàájọ́ dúró ní ẹnu ìlẹ̀kùn.
ⲑ̅ⲘⲠⲈⲢϤⲒⲀϨⲞⲘ ϦⲀ ⲚⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ ⲚⲀⲤⲚⲎ ⲞⲨ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨϢⲦⲈⲘϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲒⲤ ⲠⲒⲢⲈϤϮϨⲀⲠ ϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ϨⲒⲢⲈⲚ ⲚⲒⲢⲰⲞⲨ
10 Ará mi, ẹ fi àwọn wòlíì tí ó ti ń sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa ṣe àpẹẹrẹ ìyà jíjẹ, àti sùúrù.
ⲓ̅ϬⲒ ⲚⲞⲨⲤⲘⲞⲦ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲚⲦⲈϮⲘⲈⲦⲢⲈϤϢⲈⲠϦⲒⲤⲒ ⲚⲈⲘ ϮⲘⲈⲦⲢⲈϤⲰⲞⲨ ⲚϨⲎⲦ ⲚⲦⲈⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠϬⲤ
11 Sá à wò ó, àwa a máa ka àwọn tí ó fi ara dà ìyà sí ẹni ìbùkún. Ẹ̀yin ti gbọ́ ti sùúrù Jobu, ẹ̀yin sì rí ìgbẹ̀yìn tí Olúwa ṣe; pé Olúwa kún fún ìyọ́nú, ó sì ní àánú.
ⲓ̅ⲁ̅ϨⲎⲠⲠⲈ ⲦⲈⲚⲈⲢⲘⲀⲔⲀⲢⲒⲌⲒⲚ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲀⲘⲞⲚⲒ ⲚⲦⲞⲦⲞⲨ ⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈϮϨⲨⲠⲞⲘⲞⲚⲎ ⲚⲦⲈⲒⲰⲂ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒϪⲰⲔ ⲚⲦⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϢⲀⲚⲐⲘⲀϦⲦ ⲈⲘⲀϢⲰ ⲠⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲢⲈϤⲰⲞⲨⲚϨⲎ ⲦⲠⲈ
12 Ṣùgbọ́n ju ohun gbogbo lọ, ará mi, ẹ má ṣe ìbúra, ìbá à ṣe fífi ọ̀run búra, tàbí ilẹ̀, tàbí ìbúra-kíbúra mìíràn. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí “Bẹ́ẹ̀ ni” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni; àti “Bẹ́ẹ̀ kọ́” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ kọ́; kí ẹ má ba à bọ́ sínú ẹ̀bi.
ⲓ̅ⲃ̅ⲚϢⲞⲢⲠ ⲘⲈⲚ ⲚϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢⲀⲚⲀϢ ⲞⲨⲆⲈ ⲈϨⲢⲈⲚ ⲦⲪⲈ ⲞⲨⲆⲈ ⲈϨⲢⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ ⲞⲨⲆⲈ ⲔⲈⲀⲚⲀϢ ⲔⲈⲀⲚⲀϢ ⲘⲀⲢⲈ ⲠⲈⲦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ⲆⲈ ⲈⲢⲞⲨⲀϨⲀ ⲀϨⲀ ⲘⲘⲞⲚ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲦⲈⲘϢⲰⲠⲒ ϦⲀ ⲞⲨϨⲀⲠ
13 Inú ẹnikẹ́ni ha bàjẹ́ nínú yín bí? Jẹ́ kí ó gbàdúrà. Inú ẹnikẹ́ni ha dùn? Jẹ́ kí ó kọrin mímọ́.
ⲓ̅ⲅ̅ⲒⲤϪⲈ ⲆⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲀⲒ ϬⲒϦⲒⲤⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲘⲀⲢⲈϤⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲈⲤⲐⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲨⲚⲞϤ ⲚϨⲎⲦ ⲘⲀⲢⲈϤⲈⲢⲮⲀⲖⲒⲚ
14 Ẹnikẹ́ni ha ṣe àìsàn nínú yín bí? Kí ó pe àwọn àgbà ìjọ, kí wọ́n sì gbàdúrà sórí rẹ̀, kí wọn fi òróró kùn ún ní orúkọ Olúwa.
ⲓ̅ⲇ̅ⲒⲤϪⲈ ⲆⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲀⲒ ϢⲰⲚⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲘⲀⲢⲈϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲚⲒⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲚⲦⲈϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀⲢⲞⲨⲦⲰⲂϨ ⲈϪⲰϤ ⲈⲀⲨⲐⲀϨⲤϤ ⲚⲞⲨⲚⲈϨ ϦⲈⲚⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠϬⲤ
15 Àdúrà ìgbàgbọ́ yóò sì gba aláìsàn náà là, Olúwa yóò sì gbé e dìde; bí ó bá sì ṣe pé ó ti dẹ́ṣẹ̀, a ó dáríjì í.
ⲓ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈ ⲠⲦⲰⲂϨ ⲘⲪⲚⲀϨϮ ⲈϤⲈⲚⲞϨⲈⲘ ⲘⲪⲎ ⲈⲐⲘⲞⲔϨ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤⲈⲦⲞⲨⲚⲞⲤϤ ⲚϪⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲔⲀⲚ ⲈϢⲰⲠ ⲀϤⲒⲢⲒ ⲚϨⲀⲚⲚⲞⲂⲒ ⲈⲨⲈⲬⲀⲨ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ
16 Ẹ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín fún ara yín, kí ẹ sì máa gbàdúrà fún ara yín, kí a lè mú yín láradá. Iṣẹ́ tí àdúrà olódodo ń ṣe ní agbára púpọ̀.
ⲓ̅ⲋ̅ⲞⲨⲰⲚϨ ⲞⲨⲚ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲞⲂⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲎ ⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲰⲂϨ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ ϨⲞⲠⲰⲤ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲨϪⲀⲒ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϪⲞⲘ ϦⲈⲚⲦⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲘⲠⲒⲐⲘⲎⲒ ⲈⲤⲈⲢϨⲰⲂ
17 Ènìyàn bí àwa ni Elijah, ó gbàdúrà gidigidi pé kí òjò kí ó má ṣe rọ̀, òjò kò sì rọ̀ sórí ilẹ̀ fún ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà.
ⲓ̅ⲍ̅ⲎⲖⲒⲀⲤ ⲚⲈⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ϨⲰϤ ⲠⲈ ⲚⲢⲈϤϢⲈⲠⲘⲔⲀϨ ⲘⲠⲈⲚⲢⲎϮ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲰⲂϨ ⲚⲞⲨⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲈϢⲦⲈⲘⲐⲢⲈ ⲦⲪⲈ ϨⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲤϨⲰⲞⲨ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲒⲔⲀϨⲒ ⲚⲄϮ ⲚⲢⲞⲘⲠⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲀⲂⲞⲦ
18 Ó sì tún gbàdúrà, ọ̀run sì tún rọ̀jò, ilẹ̀ sì so èso rẹ̀ jáde.
ⲓ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲰⲂϨ ⲞⲚ ⲀⲦⲪⲈ ϮⲚⲞⲨⲘⲞⲨⲚϨⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲠⲔⲀϨⲒ ⲢⲰⲦ ⲀϤϮ ⲘⲠⲈϤⲞⲨⲦⲀϨ
19 Ará, bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ẹni kan sì yí i padà;
ⲓ̅ⲑ̅ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲞⲨⲀⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲤⲰⲢⲈⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀ ϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤⲦⲀⲤⲐⲞϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲀⲒ
20 jẹ́ kí ó mọ̀ pé, ẹni tí ó bá yí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan padà kúrò nínú ìṣìnà rẹ̀, yóò gba ọkàn kan là kúrò lọ́wọ́ ikú, yóò sì bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.
ⲕ̅ⲘⲀⲢⲈϤⲈⲘⲒ ⲚϪⲈⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲦⲀⲤⲐⲞ ⲚⲞⲨⲢⲈϤⲈⲢⲚⲞⲂⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲘⲰⲒⲦ ⲚⲦⲈⲦⲈϤⲠⲖⲀⲚⲎ ϪⲈ ϤⲚⲀⲚⲞϨⲈⲘ ⲚⲦⲈϤⲮⲨⲬⲎ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ϤⲚⲀϨⲰⲂⲤ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϪⲈⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲚⲞⲂⲒ.