< James 4 >
1 Níbo ni ogun ti wá, níbo ni ìjà sì ti wá láàrín yín? Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara yín ha kọ́ ni tí ó ń jagun nínú àwọn ẹ̀yà ara yín bí?
ⲁ̅ⲁⲣⲉ ⲡⲟⲗⲉⲙⲟⲥ ⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲑⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲉ⳿ⲙⲗⲁϧ ⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲑⲱⲛ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲙⲏ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲩⲇⲟⲛⲏ ⲛⲏⲉⲧϧⲏⲕ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲗⲟⲥ.
2 Ẹ̀yin ń fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, ẹ kò sì ní, ẹ̀yin ń pànìyàn, ẹ sì ń ṣe ìlara, ẹ kò sì le ní: ẹ̀yin ń jà, ẹ̀yin sì ń jagun; ẹ kò ní, nítorí tí ẹ̀yin kò béèrè.
ⲃ̅ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣ⳿ⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛϧⲱⲧⲉⲃ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲭⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϣⲁϣⲛⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ϣϭⲛⲏⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲡⲟⲗⲉⲙⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲉⲛ ⲉⲑⲃⲉ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⲁⲛ.
3 Ẹ̀yin béèrè, ẹ kò sì rí gbà, nítorí tí ẹ̀yin ṣì béèrè, kí ẹ̀yin kí ó lè lò ó fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara yín.
ⲅ̅ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛϭⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛⲕⲁⲕⲱⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲩⲇⲟⲛⲏ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϭⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
4 Ẹ̀yin panṣágà ọkùnrin, àti panṣágà obìnrin, ẹ kò mọ̀ pé ìbárẹ́ ayé ìṣọ̀tá Ọlọ́run ni? Nítorí náà ẹni tí ó bá fẹ́ láti jẹ́ ọ̀rẹ́ ayé di ọ̀tá Ọlọ́run.
ⲇ̅ⲛⲓⲛⲱⲓⲕ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ϯⲙⲉⲧ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲟⲩⲙⲉⲧϫⲁϫⲓ ⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲑⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⳿ϥⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛϫⲁϫⲓ ⳿ⲉⲫϯ.
5 Ẹ̀yin ṣe bí Ìwé Mímọ́ sọ lásán pé, Ẹ̀mí tí ó fi sínú wa ń jowú gidigidi lórí wa?
ⲉ̅ϣⲁⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲁⲣⲉ ϯ⳿ⲅⲣⲁⲫⲏ ϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲉ⳿ⲫⲗⲏⲟⲩ ⲓⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲫⲑⲟⲛⲟⲥ ⳿ϥϭⲓϣϣⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲫⲏⲉⲧϣⲟⲡ ⳿ⲛϧⲏⲧⲉⲛ.
6 Ṣùgbọ́n ó fún ni ní oore-ọ̀fẹ́ sí i. Nítorí náà ni ìwé mímọ́ ṣe wí pé, “Ọlọ́run kọ ojú ìjà sí àwọn agbéraga, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún àwọn onírẹ̀lẹ̀ ọkàn.”
ⲋ̅⳿ϥϯ ⲇⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⳿ϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲫϯ ⳿ϥϯ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ⲛⲓϭⲁⲥⲓϩⲏⲧ ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲑⲉⲃⲓⲏⲟⲩⲧ ⳿ϥⲛⲁϯ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ϩⲙⲟⲧ.
7 Nítorí náà, ẹ tẹríba fún Ọlọ́run. Ẹ kọ ojú ìjà sí èṣù, òun ó sì sá kúrò lọ́dọ̀ yín.
ⲍ̅ⲙⲁϭⲛⲉϫⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲫϯ ϯ ⲇⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ⲡⲓⲇⲓ⳿ⲁⲃⲟⲗⲟⲥ ⲉϥ⳿ⲉⲫⲱⲧ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ.
8 Ẹ súnmọ́ Ọlọ́run, òun ó sì súnmọ́ yín. Ẹ wẹ ọwọ́ yín mọ́, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀; ẹ sì ṣe ọkàn yín ní mímọ́, ẹ̀yin oníyèméjì.
ⲏ̅ⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲫϯ ⲉϥ⳿ⲉϧⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲙⲁⲧⲟⲩⲃⲟ ⲛⲉⲧⲉⲛϫⲓϫ ⲛⲓⲣⲉϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲙⲁⲧⲟⲩⲃⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ ϧⲁ ⲛⲓϩⲏⲧ ⲃ̅.
9 Ẹ banújẹ́, ẹ ṣọ̀fọ̀, kí ẹ sì hu fún ẹkún. Ẹ jẹ́ kí ẹ̀rín yín kí ó di ọ̀fọ̀, àti ayọ̀ yín kí ó di ìbànújẹ́.
ⲑ̅ⲁⲣⲓⲧⲁⲗⲉⲡⲱⲣⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲓϩⲏⲃⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲣⲓⲙⲓ ⲡⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲃⲓ ⲙⲁⲣⲉϥⲕⲟⲧϥ ⲉⲩϩⲏⲃⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉⲧⲉⲛⲣⲁϣⲓ ⲉⲩⲟⲕⲉⲙ.
10 Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀ níwájú Olúwa, òun ó sì gbé yín ga.
ⲓ̅ⲙⲁⲑⲉⲃⲓⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫϯ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϭⲉⲥ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
11 Ará, ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ ibi sí ara yín. Ẹni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ibi sí arákùnrin rẹ̀, tí ó ń dá arákùnrin rẹ̀ lẹ́jọ́, ó ń sọ̀rọ̀ ibi sí òfin, ó sì ń dá òfin lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ń dá òfin lẹ́jọ́, ìwọ kì í ṣe olùfẹ́ òfin, bí kò ṣe onídàájọ́.
ⲓ̅ⲁ̅⳿ⲙⲡⲉⲣⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲫⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲥⲁϫⲓ ⲡⲉϥⲥⲟⲛ ⲓⲉ ⲉϥϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲡⲉϥⲥⲟⲛ ⲁϥⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⳿ⲕϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲓⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲟⲩⲣⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲟⲩⲣⲉϥϯ ϩⲁⲡ.
12 Aṣòfin àti onídàájọ́ kan ṣoṣo ní ó ń bẹ, àní ẹni tí ó lè gbàlà tí ó sì le parun, ṣùgbọ́n ta ni ìwọ tí ó ń dá ẹnìkejì rẹ lẹ́jọ́?
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲑⲉⲧⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲣⲉϥϯϩⲁⲡ ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲧⲟⲩϫⲟ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲛⲓⲙ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ϧⲁ ⲫⲏⲉⲧϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲡⲉⲕ⳿ϣⲫⲏⲣ.
13 Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin tí ó ń wí pé, “Lónìí tàbí lọ́la àwa ó lọ sí ìlú báyìí, a ó sì ṣe ọdún kan níbẹ̀, a ó sì ṣòwò, a ó sì jèrè.”
ⲓ̅ⲅ̅ⲁⲅⲉ ϯⲛⲟⲩ ⲛⲏⲉⲧϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲫⲟⲟⲩ ⲓⲉ ⲣⲁⲥϯ ⲧⲉⲛⲛⲁϣⲉ ⲛⲁⲛ ⳿ⲉⲧⲁⲓⲡⲟⲗⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉⲛ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲉⲣⲓⲉⲃϣⲱⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲛϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ.
14 Nígbà tí ẹ̀yin kò mọ ohun tí yóò hù lọ́la. Kí ni ẹ̀mí yín? Ìkùùkuu sá à ni yín, tí ó hàn nígbà díẹ̀, lẹ́yìn náà a sì túká lọ.
ⲓ̅ⲇ̅ⲛⲏⲉⲧⲉ ⳿ⲛⲥⲉⲥⲱⲟⲩⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲑⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥⲣⲁⲥϯ ⲁϣ ⲡⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲱⲛϧ ⲁϥ⳿ⲙⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩϣⲱⲓϣ ⲉϥⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲡⲣⲟⲥ ⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲓⲧⲁ ϣⲁϥⲧⲁⲕⲟ.
15 Èyí tí ẹ̀ bá fi wí pé, “Bí Olúwa bá fẹ́, àwa yóò wà láààyè, àwa ó sì ṣe èyí tàbí èyí i nì.”
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲣⲉϣⲁⲛ Ⲡ⳪ ⲟⲩⲱϣ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲱⲛϧ ⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣ ⲫⲁⲓ ⲓⲉ ⲫⲏ.
16 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń gbéraga nínú ìfọ́nnu yín, gbogbo irú ìfọ́nnu bẹ́ẹ̀, ibi ni.
ⲓ̅ⲋ̅ϯⲛⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲧⲣⲉϥϩⲓ⳿ⲡϩⲟ ϣⲟⲩϣⲟⲩ ⲇⲉ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲥⲉϩⲱⲟⲩ.
17 Nítorí náà ẹni tí ó bá mọ rere í ṣe tí kò sì ṣe é, ẹ̀ṣẹ̀ ni fún un.
ⲓ̅ⲍ̅ⲫⲏⲉⲧⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⳿ⲉⲁⲓϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲁⲓϥ ⲟⲩⲛⲟⲃⲓ ⲛⲁϥ ⲡⲉ