< James 2 >
1 Ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí onígbàgbọ́ nínú ògo Olúwa wá Jesu Kristi, ẹ máa ṣe ojúsàájú ẹnikẹ́ni.
N kpiiba, yinba yaaba n daani ti Diedo Jesu Kilisiti yua n pia ti kpiagidi yeni, laa pundi yin ya tiendi mi gagidima bi niba siiga.
2 Nítorí bí ọkùnrin kan bá wá sí ìpéjọpọ̀ yín, pẹ̀lú òrùka wúrà àti aṣọ dáradára, tí tálákà kan sì wá pẹ̀lú nínú aṣọ èérí;
Min bagi yaala tie line: O nilo ya kua yi taanli nni ki pili wula ñoagibila, ki go yie ya tiadi n pia ti kpiagidi, o luodo mo n kua ki yie a kpacala.
3 tí ẹ̀yin sì bu ọlá fún ẹni tí ó wọ aṣọ dáradára tí ẹ sì wí pé, “Ìwọ jókòó níhìn-ín yìí ní ibi dáradára,” tí ẹ sì wí fún tálákà náà pé, “Ìwọ dúró níbẹ̀” tàbí “jókòó níhìn-ín lábẹ́ àpótí ìtìsẹ̀ mi,”
Li ya tie ke yi jigini yua n yie ya tiayiekaadi n pia ti kpiagidi ki yedi o: “Kali ne ti jigidi kaanu,” ki yedi o luodo mo ya se ne” yaaka: “Kali tiipo n taana kani”.
4 ẹyin kò ha ń dá ara yín sí méjì nínú ara yín, ẹ̀yin kò sì di onídàájọ́ tí ó ní èrò búburú bí?
Naani yii tieni mi gagidima yi yama nni ki go bigidi leni li yantiabiadili kaa?
5 Ẹ fi etí sílẹ̀, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́: Ọlọ́run kò ha ti yan àwọn tálákà ayé yìí láti jẹ́ ọlọ́rọ̀ nínú ìgbàgbọ́, àti ajogún ìjọba náà, tí ó ti ṣe ìlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ?
N kpibuadiba, cengi mani, naani U Tienu ki gandi yaaba n tie luoda ŋanduna nuni po ke ban tua piada li dandanli nni, ki go baa wan niani ke o baa pa yaaba n bua o kuli ya diema kaa?
6 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti bu tálákà kù. Àwọn ọlọ́rọ̀ kò ha ń pọ́n yin lójú bí; wọn kò ha sì ń wọ́ yín lọ sílé ẹjọ́?
Ama yinba, yi fali o luodo. Laa tie a piada kaa mabindi yi ki caani yi li bujiali kani?
7 Wọn kò ha ń sọ ọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ rere nì tí a fi ń pè yín bí?
Bani kaa sugidi ya yeŋanli n ye yi niinni?
8 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń mú olú òfin nì ṣẹ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́, èyí tí ó wí pé, “Ìwọ fẹ́ ẹni kejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ,” ẹ̀yin ń ṣe dáradára.
Yi ya kubi U Tienu diema balimaama nani lan diani maama li ŋani, mani yaama n yedi: “ŋan bua a nisaali lielo nani ŋan bua a yuli maama.”
9 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń ṣe ojúsàájú ènìyàn, ẹ̀yin ń dẹ́ṣẹ̀, a sì ń dá yín lẹ́bi nípa òfin bí arúfin.
Ama yi ya tiendi mi gagidima bi niba siiga, yi tiendi ti tuonbiadi, li balimaama mo buni ki cuo yi kelima yi miidi ma.
10 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa gbogbo òfin mọ́, tí ó sì rú ọ̀kan, ó jẹ̀bi rírú gbogbo rẹ̀.
Kelima yua n kubi li balimaama ki nan miidi ba balimayenma bebe, pia i tagili mi kuli po.
11 Nítorí ẹni tí ó wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà,” òun ni ó sì wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.” Ǹjẹ́ bí ìwọ kò ṣe panṣágà, ṣùgbọ́n tí ìwọ pànìyàn, ìwọ jásí arúfin.
Kelima yua n yedi: “ŋan da conbi” wani n go yedi: “ŋan da kpa o nilo” moko. Lanwani a yaa conbi ki nan kpa o nilo, a tua li balimaama miidikoa.
12 Ẹ máa sọ̀rọ̀, ẹ sì máa hùwà, bí àwọn tí a ó fi òfin òmìnira dá lẹ́jọ́.
Yin ya maadi mani ki go tiendi, ki bani ke U Tienu baa jia leni yi ti buudi ki ŋua leni ya balimaama n puuni mi faabima.
13 Nítorí ẹni tí kò ṣàánú, ni a ó ṣe ìdájọ́ fún láìsí àánú; àánú ń ṣògo lórí ìdájọ́.
U Tienu ya jia ti buudi ya yogunu, o kan gbadi mi niŋima yaa nilo n kaa den gbadi mi niŋima o lielo po yaapo. Mi niŋigbadima paani li bujiali.
14 Èrè kí ni ó jẹ́, ará mi, bí ẹni kan wí pé òun ní ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n tí kò ní àwọn iṣẹ́ láti fihan? Ìgbàgbọ́ náà lè gbà á là bí?
N kpiiba, o nilo ya yedi ke o pia li dandanli ki naa pia a tuona, li pia be fuoma? Naani o dandanli yeni baa fidi ki tindi o bi?
15 Bí arákùnrin tàbí arábìnrin kan bá wà ní àìní aṣọ, tí ó sì ṣe àìní oúnjẹ òòjọ́,
Li ya tie ke yi siiga joa bi pua luo ti tiayiekaadi ki go luo daali kuli bonjekaala,
16 tí ẹni kan nínú yín sì wí fún pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí ara rẹ kí ó má ṣe tutù, kí ó sì yó,” ṣùgbọ́n ẹ kò fi nǹkan wọ̀n-ọn-nì ti ara ń fẹ́ fún wọn; èrè kí ni ó jẹ́?
ke yi siiga yendo yedi o: “Ya kuni leni mi yanduanma, ki ban yeli mi fantama ki go je ki guo,” ama ki naa puni o yaala n tie o yema po tiladi, li pia be fuoma?
17 Bẹ́ẹ̀ sì ni ìgbàgbọ́, bí kò bá ní iṣẹ́ rere, ó kú nínú ara rẹ̀.
Li tie yenma leni li dandanli: li yaa pia tuona li kpe.
18 Ṣùgbọ́n ẹnìkan lè wí pé, “Ìwọ ní ìgbàgbọ́, èmi sì ní iṣẹ́.” Fi ìgbàgbọ́ rẹ hàn mí ní àìsí iṣẹ́, èmi ó sì fi ìgbàgbọ́ mi hàn ọ́ nípa iṣẹ́ rere mi.
Ama nilo ya yedi: “Fini a pia li dandanli, n mo pia a tuona” n baa yedi o: “waani a dandanli yaali n kaa pia tuona n mo baa waani a n dandanli kelima n tuona po.”
19 Ìwọ gbàgbọ́ pé Ọlọ́run kan ní ó ń bẹ; ó dára! Àwọn ẹ̀mí èṣù pẹ̀lú gbàgbọ́ bẹ́ẹ̀, wọ́n sì wárìrì.
A daani ke U Tienu ye ki tie yendo bebe, a tieni ke li ŋani. Ama mu cicibiadimu moko daani yeni ki jie ki digibi.
20 Ṣùgbọ́n, ìwọ aláìmòye ènìyàn, ìwọ ha fẹ́ ní ìdánilójú pé, ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ rere asán ni?
Fini o yanluodaano na, naani a bua ki bandi ke ya dandanli n ki pia a tuona tie fanma bi?
21 Kí ha í ṣe nípa iṣẹ́ ni a dá Abrahamu baba wa láre, nígbà tí ó fi Isaaki ọmọ rẹ̀ rú ẹbọ lórí pẹpẹ?
Naani ti yaaja Abalaŋama ki den baa li moamoasaali kelima a tuona po wan den padi o biga Isaaka li padibinbinli po kaa?
22 Ìwọ rí i pé ìgbàgbọ́ rẹ bá iṣẹ́ rìn, àti pé nípa iṣẹ́ rere ni a sọ ìgbàgbọ́ di pípé.
A laa ke o dandanli den taani ki yegi leni o tuona, ke o tuona yeni mo den teni ke o dandanli ŋani ki dagidi cain.
23 Ìwé Mímọ́ sì ṣẹ́ tí ó wí pé, “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un,” a sì pè é ní ọ̀rẹ́ Ọlọ́run.
Yeni i Diani n yedi yaala tieni: “Abalaŋama den daani U Tienu ke U Tienu den coadi opo la ke li tie teginma.” Bi den yi o U Tienu danli.
24 Ǹjẹ́ ẹ̀yin rí i pé nípa iṣẹ́ rere ni à ń dá ènìyàn láre, kì í ṣe nípa ìgbàgbọ́ nìkan.
Yi laa, o nilo baa li moamoansaali kelima o tuona po, laa tie kelima o dandanli bebe po ka.
25 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú kí a dá Rahabu panṣágà láre nípa iṣẹ́ bí, nígbà tí ó gba àwọn ayọ́lẹ̀wò, tí ó sì rán wọn jáde gba ọ̀nà mìíràn?
Li go tie yeni Laŋaba li poconconli po. O den baa li moamoansaali o tuona po, kelima o den ga bi tondiba cangu ki teni ke bi tagini santo ki kuni.
26 Nítorí bí ara ní àìsí ẹ̀mí ti jẹ́ òkú, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú ni ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ jẹ́ òkú.
Lanwani, nani ya gbannandi n ki pia naano n kpe maama, ya dandanli n ki pia tuona moko kpe yene.