< James 1 >

1 Jakọbu, ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti ti Jesu Kristi Olúwa, Sí àwọn ẹ̀yà méjìlá tí ó fọ́n káàkiri, orílẹ̀-èdè: Àlàáfíà.
Iacov, rob al lui Dumnezeu și al Domnului Isus Cristos, celor douăsprezece triburi care sunt împrăștiate: Salutare!
2 Ẹ̀yin ará mi, nígbà tí ẹ̀yin bá bọ́ sínú onírúurú ìdánwò, ẹ ka gbogbo rẹ̀ sí ayọ̀;
Socotiți totul a fi bucurie, frații mei, când cădeți în diverse ispitiri,
3 nítorí tí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìdánwò ìgbàgbọ́ yín ń ṣiṣẹ́ sùúrù.
Știind că încercarea credinței voastre lucrează răbdare.
4 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí sùúrù kí ó ṣiṣẹ́ àṣepé, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ́ pípé àti aláìlábùkù tí kò ṣe aláìní ohunkóhun.
Dar lăsați răbdarea să își aibă lucrarea desăvârșită, ca să fiți desăvârșiți și întregi, nefiind lipsiți în nimic.
5 Bí ó bá ku ọgbọ́n fún ẹnikẹ́ni, kí ó béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run ẹni tí fi fún gbogbo ènìyàn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, tí kì í sì ka àlébù sí; a ó sì fi fún un.
Dar dacă unuia dintre voi îi lipsește înțelepciunea, să o ceară de la Dumnezeu, care dă tuturor cu generozitate și nu reproșează, și îi va fi dată.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun bá béèrè ní ìgbàgbọ́, ní àìṣiyèméjì rárá. Nítorí ẹni tí ó ń sé iyèméjì dàbí ìgbì omi Òkun, tí à ń ti ọwọ́ afẹ́fẹ́ bì síwá bì sẹ́yìn, tí a sì ń rú u sókè.
Dar să ceară în credință, neclătinându-se în nimic. Pentru că cel ce se clatină seamănă cu un val al mării împins de vânt și aruncat încoace și încolo.
7 Kí irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ má ṣe rò pé, òun yóò rí ohunkóhun gbà lọ́wọ́ Olúwa;
De aceea să nu gândească omul acela că va primi ceva de la Domnul.
8 Ó jẹ ènìyàn oníyèméjì aláìlèdúró ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo.
Un om șovăitor este nestatornic în toate căile lui.
9 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí arákùnrin tí ó ń ṣe onírẹ̀lẹ̀ máa ṣògo ní ipò gíga.
Dar să se bucure fratele de rând în aceea că el este înălțat.
10 Àti ọlọ́rọ̀, ní ìrẹ̀sílẹ̀, nítorí bí ìtànná koríko ni yóò kọjá lọ.
Iar bogatul în aceea că este înjosit, pentru că va trece ca floarea ierbii.
11 Nítorí oòrùn là ti òun ti ooru gbígbóná yóò gbẹ́ koríko, ìtànná rẹ̀ sì rẹ̀ dànù, ẹwà ojú rẹ̀ sì parun: bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ọlọ́rọ̀ yóò ṣègbé ní ọ̀nà rẹ̀.
Fiindcă a răsărit soarele cu arșița și usucă iarba și floarea ei cade și frumusețea înfățișării ei piere: astfel și bogatul se va ofili în căile lui.
12 Ìbùkún ni fún ọkùnrin tí ó fi ọkàn rán ìdánwò; nítorí nígbà tí ó bá yege, yóò gba adé ìyè, tí Olúwa ti ṣèlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ.
Binecuvântat este omul care îndură ispita, pentru că, după ce este încercat, va primi coroana vieții, pe care a promis-o Domnul celor ce îl iubesc.
13 Kí ẹnikẹ́ni tí a dánwò kí ó má ṣe wí pé, “Láti ọwọ́ Ọlọ́run ni a ti dán mi wò.” Nítorí a kò lè fi búburú dán Ọlọ́run wò, òun náà kì í sì í dán ẹnikẹ́ni wò;
Să nu spună cineva când este ispitit: Sunt ispitit de Dumnezeu. Fiindcă Dumnezeu nu poate fi ispitit de rău, nici nu ispitește el pe nimeni,
14 ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni a ń dánwò nígbà tí a bá fi ọwọ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara rẹ̀ fà á lọ tí a sì tàn án jẹ.
Ci fiecare este ispitit, când este atras de propria lui poftă și ademenit.
15 Ǹjẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ nígbà tí ó bá lóyún a bí ẹ̀ṣẹ̀, àti ẹ̀ṣẹ̀ náà nígbà tí ó bá dàgbà tán, a bí ikú.
Apoi, după ce pofta a conceput, naște păcat; iar păcatul, odată înfăptuit, naște moarte.
16 Kí a má ṣe tàn yín jẹ, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́.
Nu vă rătăciți preaiubiții mei frați!
17 Gbogbo ẹ̀bùn rere àti gbogbo ẹ̀bùn pípé láti òkè ni ó ti wá, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ baba ìmọ́lẹ̀ wá, lọ́dọ̀ ẹni tí kò lè yípadà gẹ́gẹ́ bí òjìji àyídà.
Fiecare dar bun și fiecare dar desăvârșit este de sus, coborând de la Tatăl luminilor, la care nu este schimbare, nici umbră de întoarcere.
18 Ó pinnu láti fi ọ̀rọ̀ òtítọ́ bí wa kí àwa kí ó le jẹ́ àkọ́so nínú ohun gbogbo tí ó dá.
Din voia lui ne-a născut el prin cuvântul adevărului, ca să fim un anumit fel de prime roade ale creaturilor sale.
19 Kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́; jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn kí ó máa yára láti gbọ́, kí ó lọ́ra láti fọhùn, kí ó si lọ́ra láti bínú;
De aceea, preaiubiții mei frați, fiecare om să fie grăbit la auzire, încet la vorbire, încet la furie;
20 nítorí ìbínú ènìyàn kì í ṣiṣẹ́ òdodo irú èyí tí Ọlọ́run ń fẹ́.
Fiindcă furia unui om nu lucrează dreptatea lui Dumnezeu.
21 Nítorí náà, ẹ lépa láti borí gbogbo èérí àti ìwà búburú tí ó gbilẹ̀ yíká, kí ẹ sì fi ọkàn tútù gba ọ̀rọ̀ náà tí a gbìn, tí ó lè gba ọkàn yín là.
De aceea puneți deoparte toată murdăria și revărsarea răutății și primiți cu blândețe cuvântul altoit, care este în stare să vă salveze sufletele.
22 Ẹ má kan jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rọ̀ náà lásán, kí ẹ má ba à ti ipa èyí tan ara yín jẹ́. Ẹ ṣe ohun tí ó sọ.
Fiți așadar înfăptuitori ai cuvântului și nu doar ascultători [ai lui], înșelându-vă pe voi înșivă.
23 Nítorí bí ẹnikẹ́ni bá jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí kò sì jẹ́ olùṣe, òun dàbí ọkùnrin tí ó ń ṣàkíyèsí ojú ara rẹ̀ nínú dígí
Pentru că dacă vreunul este ascultător al cuvântului și nu înfăptuitor, el este asemănător unui om care își privește fața naturală în oglindă;
24 nítorí, lẹ́yìn tí ó bá ti ṣàkíyèsí ara rẹ̀, tí ó sì bá tirẹ̀ lọ, lójúkan náà òun sì gbàgbé bí òun ti rí.
Fiindcă se privește pe sine însuși și pleacă și uită imediat ce fel de om era.
25 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń wo inú òfin pípé, òfin òmìnira ni, tí ó sì dúró nínú rẹ̀, tí òun kò sì jẹ́ olùgbọ́ tí ń gbàgbé bí kò ṣe olùṣe rẹ̀, òun yóò jẹ́ alábùkún nínú iṣẹ́ rẹ̀.
Dar oricine privește cu atenție în legea desăvârșită a libertății și continuă în ea, el, nefiind un ascultător uituc, ci un înfăptuitor al faptei, acesta va fi binecuvântat în fapta lui.
26 Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ń sin Ọlọ́run nígbà tí kò kó ahọ́n rẹ̀ ní ìjánu, ó ń tan ọkàn ara rẹ̀ jẹ, ìsìn rẹ̀ sì jẹ́ asán.
Dacă cineva printre voi pare să fie religios și nu își înfrânează limba, ci își înșală inima, religia acestuia este deșartă.
27 Ìsìn mímọ́ àti aláìléèérí níwájú Ọlọ́run àti Baba ni èyí, láti máa bojútó àwọn aláìní baba àti àwọn opó nínú ìpọ́njú wọn, àti láti pa ara rẹ̀ mọ́ láìlábàwọ́n kúrò nínú ayé.
Religia pură și neîntinată înaintea lui Dumnezeul și Tatăl este aceasta: A cerceta pe cei fără tată și văduve în nenorocirea lor, și a se ține pe sine însuși nepătat de lume.

< James 1 >