< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Umbono kaIsaya indodana kaAmozi, awubona ngoJuda leJerusalema, ensukwini zaboUziya, uJothamu, uAhazi, uHezekhiya, amakhosi akoJuda.
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Zwanini, mazulu, ubeke indlebe, mhlaba, ngoba iNkosi isikhulumile, yathi: Ngondlile ngakhulisa abantwana, kodwa bona bangivukele.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Inkabi iyamazi umniniyo, lobabhemi umkolo womnikazi wakhe; kodwa uIsrayeli kazi, abantu bami kabaqedisisi.
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Hawu, isizwe esonayo, abantu abasindwa yibubi, inzalo yabenzi bobubi, abantwana abonakalisayo! Bayitshiyile iNkosi, bamdelele oNgcwele kaIsrayeli, bahlehlele nyovane.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
Lizatshayelwani futhi? Belizaqhubeka livukela; ikhanda lonke liyagula, lenhliziyo yonke ibuthakathaka.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
Kusukela kungaphansi yonyawo kuze kufike ekhanda kakulandawo ephilileyo kukho, kodwa izilonda lemivimvinya lamanxeba ophayo; kakukhanywanga, kakubotshwanga, kakuthanjiswanga ngamafutha.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
Ilizwe lakini liyincithakalo, imizi yenu itshiswe ngomlilo, umhlaba wenu abezizwe bawudla phambi kwenu, njalo kulencithakalo, njengokugenqulwa ngabemzini.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
Indodakazi yeZiyoni isele-ke njengedumba esivinini, njengengalane ensimini yamakhomane, njengomuzi ovinjezelweyo.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
Uba iNkosi yamabandla ibingasitshiyelanga insali eyingcosana, besizakuba njengeSodoma, sifanane leGomora.
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
Zwanini ilizwi leNkosi, babusi beSodoma, libeke indlebe kumlayo kaNkulunkulu wethu, bantu beGomora.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
Buyini kimi ubunengi bemihlatshelo yenu? itsho iNkosi. Ngenelisiwe yiminikelo yokutshiswa yezinqama langamahwahwa okunonisiweyo; legazi lamajongosi lelamawundlu lelezimpongo kangithokozi ngalo.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
Lapho lisizabonakala phambi kwami, ngubani obize lokhu esandleni senu, ukugxoba amaguma ami?
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Lingabe lisaletha umnikelo oyize; impepha iyisinengiso kimi; ukuthwasa kwenyanga, lesabatha, ukubizwa kwenhlangano, ngingekumele; kuyisiphambeko, ngitsho umhlangano onzulu.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
Umphefumulo wami uyakuzonda ukuthwasa kwezinyanga zenu lemikhosi yenu emisiweyo; kungumthwalo kimi, sengikhathele yikukuthwala.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
Lalapho liselula izandla zenu ngizalifihlela amehlo ami; njalo nxa lisandisa umkhuleko kangiyikuzwa; izandla zenu zigcwele igazi.
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Gezani, lizihlambulule; susani ububi bezenzo zenu phambi kwamehlo ami; yekelani ukwenza okubi;
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
fundani ukwenza okuhle; dingani isahlulelo; sizani ocindezelweyo; yehlulelani intandane; melani umfelokazi.
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Wozani khathesi, siqondisane, itsho iNkosi; loba izono zenu zinjengokubomvu gebhu, zizakuba mhlophe njengeliqhwa elikhithikileyo; loba zibomvu njengokubomvu kakhulu, zizakuba njengoboya bezimvu.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
Uba livuma lilalela, lizakudla okuhle kwelizwe;
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
kodwa uba lisala libe lenkani, lizadliwa yinkemba; ngoba umlomo weNkosi ukhulumile.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
Yeka, umuzi othembekileyo usube liwule! Wawugcwele isahlulelo, ukulunga kwakuhlezi kuwo, kodwa khathesi ababulali.
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Isiliva sakho sesibe ngamanyele; iwayini lakho laxubana lamanzi.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Iziphathamandla zakho zingabahlamuki labangane bamasela; ngulowo lalowo uthanda isipho, azingele izivalamlomo; kazehluleli izintandane, lendaba yomfelokazi kayifiki kuzo.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
Ngakho itsho iNkosi, iNkosi yamabandla, oLamandla wakoIsrayeli: E, ngizaziduduza ngezitha zami, ngiziphindisele kwabamelana lami.
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
Ngizabuyisela isandla sami phezu kwakho, ngicwengisise amanyele akho, ngisuse yonke ingcekeza yokucwengwa kwakho.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
Ngizabuyisela abahluleli bakho njengekuqaleni, labeluleki bakho njengakuqala; emva kwalokho ubizwe ngokuthi ngumuzi wokulunga, umuzi othembekileyo.
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
IZiyoni izahlengwa ngesahlulelo, labaphendukayo bayo ngokulunga.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
Lokwephulwa kwabaphambuki lokwezoni kuzakuba kanyekanye, labadela iNkosi baqedwe.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
Ngoba bazakuba lenhloni ngezihlahla zama-okhi elaliziloyisa, liyangeke ngezivande elizikhethileyo.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
Ngoba lizakuba njengesihlahla se-okhi omahlamvu aso ayabuna, lanjengesivande esingelamanzi.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Njalo olamandla uzakuba lifilakisi eliyizibi, lomenzi walo abe yinhlansi; njalo kuzakutsha kokubili kanyekanye, kungabi khona ocitshayo.

< Isaiah 1 >