< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Umbono omayelana ngoJuda leJerusalema owabonwa ngu-Isaya indodana ka-Amozi ensukwini zokubusa kuka-Uziya, loJothamu, lo-Ahazi loHezekhiya amakhosi akoJuda.
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Zwanini, mazulu! Lalelani, mhlaba! Ngoba uThixo usekhulumile: “Ngondla abantwana ngabakhulisa, kodwa sebengihlamukele.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Inkabi iyamazi umniniyo, lobabhemi uyasazi isibaya somnikazi wakhe, kodwa u-Israyeli kazi, abantu bami kabaqedisisi.”
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Maye kuso isizwe esonayo, abantu abathwele amacala, inzalo yabenza okubi, abantwana abaxhwalileyo! Sebemlahlile uThixo; bamdelele oNgcwele ka-Israyeli, bamfulathela.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
Kungani kumele litshaywe futhi? Kungani liqhubeka ngokuhlamuka? Ikhanda lakho lonke lilimele, yonke inhliziyo yakho ihlukuluziwe.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
Kusukela ngaphansi kwentende yonyawo lwakho kusiya esicholo sekhanda lakho akukho kuphelela, kodwa izilonda lemvivinya kuphela, kanye lamanxeba; akugeziswanga, akubotshwanga kumbe kwathanjiswa ngamafutha.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
Ilizwe lenu lichithekile, amadolobho enu atshiswa ngomlilo, umhlaba wenu uphundlwa ngabezizweni, phambi kwenu uqobo, uchitheka njengalapho udilizwa ngabezizweni.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
Indodakazi yaseZiyoni isele njengedumba esivinini, njengendlwana ensimini yamajodo, njengedolobho elihonqolozelweyo.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
Aluba uThixo uSomandla kasitshiyelanga abalutshwana abasindayo, sasizakuba njengeSodoma; sasizafana leGomora.
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
Zwanini ilizwi likaThixo, lina babusi baseSodoma, lalelani umthetho kaNkulunkulu wethu, lina bantu baseGomora!
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
“Ubunengi bemihlatshelo yenu buyini kimi?” kutsho uThixo. “Ngileminikelo yokutshiswa edlula efunekayo, eyenqama lamahwahwa ezifuyo ezinonisiweyo; igazi lenkunzi, lelamawundlu lelembuzi kalingithokozisi.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
Lapho lisiza phambi kwami, ngubani othe linyathele amaguma ami na?
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Yekelani ukuletha iminikelo eyize! Impepha yenu iyisinengiso kimi. Angingeke ngibekezelele imbuthano yenu yobubi, eyokuThwasa kweNyanga, amaSabatha lemihlangano.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
Umphefumulo wami uyawazonda amadili enu okuthwasa kwezinyanga lemikhosi yenu emisiweyo. Sekube ngumthwalo kimi; sengikhathele ngokukuthwala.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
Lapho lichaya izandla zenu likhuleka, ngizalifihlela amehlo ami; loba selikhuleka imikhuleko eminengi, angiyikulalela. Izandla zenu zigcwele igazi!
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Gezani libe ngabahlambulukileyo. Susani izenzo zenu ezimbi phambi kobuso bami; yekelani ukwenza okubi.
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
Fundani ukwenza okulungileyo; funani ukwahlulela okuhle. Khuthazani abancindezelweyo. Vikelani izintandane; lamulelani umfelokazi.
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Wozani, siqondisane sindawonye,” kutsho uThixo. “Lanxa izono zenu zibomvu gebhu, zizakuba mhlophe njengonqwaqwane, loba zibomvu njengegazi, zizakuba njengoboya bezimvu.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
Nxa livuma njalo lilalela, lizakudla okuhle kwelizwe;
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
kodwa nxa linqaba, lihlamuka, lizadliwa yinkemba.” Ngoba umlomo kaThixo usukhulumile.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
Khangelani ukuthi idolobho elithembekileyo seliphenduke laba yisifebe kanjani! Lake lagcwala ngokufaneleyo; ukulunga kwakuhlala kulo, kodwa khathesi sekuhlala ababulali!
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Isiliva senu sesingamanyele, iwayini lenu elihle selihlanganiswe lamanzi.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Ababusi benu bangabahlamuki, abangane bamasela; bonke bathanda izivalamlomo, bafune izipho. Izintandane kabazivikeli; indaba yomfelokazi kayifiki kibo.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
Ngakho-ke iNkosi, uThixo uSomandla, uMninimandla ka-Israyeli, uthi: “Yebo! Ngizabhodlisela ezitheni zami, ngibuye ngiphindisele kwabayizitha zami.
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
Ngizaphakamisela isandla sami kini; ngizawahlambulula ngokupheleleyo amanyele enu, ngisuse lakho konke ukungcola kwenu.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
Ngizabuyisa abehluleli benu njengezinsukwini zakudala, labeluleki benu njengasekuqaleni. Muva uzabizwa ngokuthi iDolobho Lokulunga, iDolobho Elithembekileyo.”
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
IZiyoni izahlengwa ngemfanelo, abaphendukayo bayo bahlengwe ngokulunga.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
Kodwa abahlamuki lezoni bazachithwa, lalabo abalahla uThixo bazabhubha.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
“Lizayangeka ngenxa yezihlahla zomʼokhi ezingcwele elazithokozisa ngazo. Lizadana ngamasimu elawakhethayo.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
Lizafana lomʼokhi olamahlamvu asebuna, lanjengensimu engelamanzi.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Indoda elamandla izafana lencwathi, umsebenzi wayo ufane lenhlansi; kokubili kuzakutsha kanyekanye, kungekho ozacitsha umlilo.”

< Isaiah 1 >