< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Ti Sirmata ni Isaias a putot ni Amos, a nakitana maipapan iti Juda ken Jerusalem, kadagidi al-aldaw da Uzzias, Jotam, Acaz ken Ezekias a nagbalin nga ar-ari ti Juda.
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Dumngegkayo a langlangit, ken denggem, daga; ta nagsao ni Yahweh: “Nangaywan ken nangpadakkelak kadagiti ubbing, ngem nagsukirda kaniak.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Ammo ti baka ti akin-kukua kenkuana, ken ammo ti asno iti pagpakanan ti amona, ngem saan nga ammo ti Israel, awan pannakaawat ti Israel.”
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Asika pay a nasion, managbasol, tattao a nailumlom iti kinadangkes, anak dagiti managdakdakes, annak nga agtigtignay a sidadakes! Tinallikudanda ni Yahweh, linaisda ti Nasantoan a Dios ti Israel, pinagbalinda a gangannaet dagiti bagbagida manipud kenkuana.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
Apay ketdin a ti pakabautanyo ti birbirukenyo? Apay ta itultuloyyo ti panagsukiryo? Ti sibubukel nga ulo ket masakit, ti sibubukel a puso ket nakapuy.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
Manipud iti dapan agingga iti ulo, awan ti paset a saan a nadangran: pasig a sugsugat, litlitem, ken silulukat a sugsugat; saanda pay a nagserra, nadalusan, nabedbedan, wenno saan pay a naagasan iti lana.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
Nadadael ti pagilianyo; napuoran dagiti siudadyo, dagiti taltalonyo-iti presensiayo-daddadaelen dagitoy dagiti ganggannaet-nadadael ken napanawan, pinarmek dagiti ganggannaet.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
Napanawan ti anak ti Sion a kasla kalapaw iti maysa a kaubasan, kasla paglinungan iti nakaimulaan dagiti pipino, kasla nalakub a siudad.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
No saan a nagibati ni Yahweh a Mannakabalin-amin iti bassit kadatayo, nagbalintayo koman a kasla iti Sodoma, mabalin a nagbalintayo koman a kasla iti Gomora;
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
Denggenyo ti sao ni Yahweh, dakayo a mangiturturay iti Sodoma; dumngegkayo iti linteg ti Diostayo, dakayo a tattao iti Gomora:
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
“Ania ngay koma ti serbi kaniak dagiti adu a sagsagutyo?” kinuna ni Yahweh. “Naumaakon kadagiti daton a mapuoran a kalakian a karnero, ken iti taba dagiti napalukmeg nga ay-ayup; ken saanko a pagragsakan ti dara dagiti bulog a baka, karnero, wenno kalding.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
No kasta nga umaykayo dumatag iti sangoanak, siasino ti nangkiddaw kadakayo iti daytoy, a baddekanyo dagiti paraangak?
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Saankayon a mangiyeg kadagiti awan serserbina a sagsagut; makarimon kaniak ti insenso; ti panangrambakyo iti baro a bulan ken panagtitiponyo iti Aldaw ti Panaginana-saanko a maanusan no kasta nga agtitiponkayo gapu kadagiti dakes nga ar-aramidenyo.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
Kagurak ti panangrambakyo iti baro a bulan ken dagiti naikeddeng a fiestayo; dadagsen dagitoy kaniak; nabannogakon a mangib-ibtur kadagitoy.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
Isu a tunggal ingatoyo dagiti imayo nga agkararag, ilingedko dagiti matak kadakayo; uray no mangipaaykayo iti adu a karkararag, saanakto a dumngeg; napno iti dara dagiti imayo.
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Agbuggokayo, dalusanyo dagiti bagbagiyo; ikkatenyo dagiti dakes nga aramidyo manipud iti imatangko; isardengyo ti kinadakesyo;
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
sursuroenyo ti agaramid iti naimbag; ipakatyo ti hustisia, tulunganyo dagiti maidaddadanes, ikalinteganyo dagiti ulila iti ama, salaknibanyo dagiti balo.”
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
“Umaykayo ita, ta aglilinnawagtayo,” kuna ni Yahweh; “uray no dagiti basolyo ket kasla naraniag a nalabaga, pumurawdanto a kasla niebe; uray no nalabagada a kasla karmesi, kasladanto kapuraw iti dutdot.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
No natulok ken natulnogkayo, kanenyonto ti naimbag nga apit iti daga.
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
ngem no agkedked ken agsukirkayo, alun-onennakayonto ti kampilan,” ta ti ngiwat ni Yahweh ti nangisao iti daytoy.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
Nagkas-angen ta nagbalinen a balangkantis ti napudno a siudad! Napnoan isuna iti hustisia- napnoan isuna iti kinalinteg, ngem ita napnoan isunan kadagiti mammapatay.
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Ti pirakmo ket nagbalin a narugit, ti arakmo ket nalaokan iti danum.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Dagiti prinsipem ket nasukir ken kakadua dagiti mannanakaw; pagaayat ti amin ti pasuksok ken gunguna. Saanda nga ikalkalintegan dagiti ulila iti ama, ken dagiti darum dagiti balo ket saan a makagteng kadakuada.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
Isu a daytoy ti pakaammo ti Apo, ni Yahweh a Mannakabalin-amin, a Mannakabalin a Dios ti Israel: Asida pay! Agibalesakto kadagiti kabusorko, ket balsek dagiti kabusorko;
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
iturongkonto ti imak a maibusor kadakayo, dalusak dagiti rugityo, ken ikkatek amin ti kinarugityo.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
Isublikto dagiti ukomyo a kas idi un-unana, ken dagiti mammagbagayo a kas idi punganay; kalpasan dayta, maawagankanto a siudad ti kinalinteg, maysa a napudno nga ili.”
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
Masubbotto ti Sion babaen iti hustisia, ken dagiti tattaona nga agbabawi babaen iti kinalinteg.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
Madadaelto a sangsangkamaysa dagiti nasukir ken managbasol, ken mapapatayto dagiti tumallikud kenni Yahweh.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
“Ta mabainkayonto gapu kadagiti nasagradoan a lugo a kaykayo a tinarigagayanyo, ket mabainankayto gapu kadagiti minuyongan a piniliyo.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
Ta kaiyariganyonto ti kayo alugo a magango dagiti bulongna, ken kasla minuyongan nga awan iti danumna.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Ti napigsa a tao ket kaslanto nagango a kayo ken ti aramidna ket kas iti risak; mapuoranda nga agpada, ket awanto ti mang-iddep kadakuada.”

< Isaiah 1 >