< Isaiah 8 >

1 Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Och Herren sade till mig: Tag dig ett stort bref, och skrif deruti med en menniskos styl: Röfva snart; hasta till byte.
2 Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
Och jag tog till mig tu trogen vittne, Presten Uria, och Zacharia, Jeberechia son;
3 Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Och gick till ena Prophetisso; hon vardt hafvandes, och födde en son; och Herren sade till mig: Kalla honom: Röfva snart; hasta till byte.
4 Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
Ty förr än pilten skall kunna säga: Käre fader, kära moder; skall Damascos magt och Samarie byte borttaget varda, genom Konungen af Assyrien.
5 Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
Och Herren talade ytterligare med mig, och sade:
6 “Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
Efter detta folket föraktar det vattnet i Siloa, hvilket så stilla löper, och tröster uppå Rezin och Remalia son;
7 ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
Si, så skall Herren låta komma öfver dem starkt och mycket strömvatten; nämliga Konungen af Assyrien, och all hans härlighet, att de skola fara öfver alla deras bäcker, och gå öfver alla deras stränder;
8 yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
Och skola infalla uti Juda, och flöda, och gå öfver, tilldess att de räcka upp till halsen; och skola utsträcka sina vingar, så att de uppfylla ditt land, o ImmanuEl, så vidt som det är.
9 Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
Varer vrede, I folk, och gifver likväl flyktena; hörer, I alle som ären i fjerran land, ruster eder, och gifver dock flyktena; ruster eder, och gifver dock flyktena.
10 Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
Besluter ett råd, och der varde intet af, talens vid, och det bestå intet; ty här är ImmanuEl.
11 Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
Ty så säger Herren till mig, lika som han fattade mig vid handena, och underviste mig, att jag icke skulle vandra på detta folks väg, och säger:
12 “Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
I skolen icke säga: Förbund. Detta folk talar om intet annat, utan om förbund. Frukter eder icke såsom de göra, och grufver eder icke;
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
Utan helger Herran Zebaoth; honom låter vara edor fruktan och förskräckelse;
14 Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
Så skall han varda en helgelse; men en stötesten och en förargelseklippa dem tvem Israels husom, Jerusalems inbyggarom till snaro och fall;
15 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
Så att månge af dem skola derpå stöta sig, falla och sönderkrossas, besnärjas och fångne varda.
16 Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Bind samman vittnesbördet; försegla lagen intill mina lärjungar.
17 Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
Ty jag hoppas uppå Herran, den sitt anlete för Jacobs hus bortgömt hafver; men jag vänter efter honom.
18 Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
Si, här är jag, och barnen som Herren mig gifvit hafver, till ett tecken och under i Israel, af Herranom Zebaoth, den der bor på bergena Zion.
19 Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
Men då de säga till eder: I måsten fråga af spåmän och tecknatydare, de der mycket tala och disputera, så skolen I säga: Skall icke ett folk fråga sin Gud? Skall man fråga de döda om de lefvande?
20 Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
Ja, efter lag och vittnesbörd; om de det icke säga, så skola de icke få morgonrodnan;
21 Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
Utan skola gå, omkring i landena slagne och hungroge; men när de hunger lida, så skola de vrede varda, och banna sinom Konung och sinom Gud, och se upp.
22 Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.
De skola ock se neder på Jordena, och intet finna annat än bedröfvelse och mörker; ty de äro förmörkrade i ångest, och gå ville i mörkret.

< Isaiah 8 >