< Isaiah 8 >

1 Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
I rzekł Pan do mnie: Weźmij sobie księgi wielkie, a napisz na nich pismem człowieczem: Pospiesz się do łupu, pokwap się do korzyści.
2 Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
Tedym wziął sobie za świadków wiernych Uryjasza kapłana, i Zacharyjasza, syna Jeberechyjaszowego.
3 Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Wtemem przystąpił do prorokini, która począwszy porodziła syna. I rzekł Pan do mnie: Nazów imię jego: Pospiesz się do łupu, pokwap się do korzyści.
4 Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
Albowiem niżeli będzie umiało to dziecię wołać: Ojcze mój i matko moja, lud króla Assyryjskiego pobierze bogactwa Damaszku, i łupy Samaryi.
5 Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
Nadto rzekł jeszcze Pan do mnie, mówiąc:
6 “Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
Ponieważ wzgardził lud ten wody Syloe, które cicho płyną, a waseli się z Rasyna, i syna Romelijaszowego:
7 ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
Przetoż oto Pan przywiedzie na nich wody rzeki gwałtownej i wielkiej, to jest króla Assyryjskiego, i wszystkę sławę jego, tak, że wystąpi ze wszystkich strumieni swoich, a wyleje ze wszystkich brzegów swoich.
8 yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
Pociecze i przez ziemię Judzką, wyleje a rozejdzie się, aż do szyi wzbierze; a rozszerzone skrzydła jego napełnią szerokość ziemi twojej, o Immanuelu!
9 Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
Zbierajcie się narody, wszakże potłumione będziecie. Przyjmujcie w uszy wszyscy w dalekiej ziemi; przepaszcie się, wszakże potłumieni będziecie; przepaszcie się, wszakże potłumieni będziecie.
10 Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
Wnijdźcie w radę, a będzie rozerwana; namówcie się, a nie ostoi się; bo Bóg z nami.
11 Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
Tak bowiem Pan rzekł do mnie, ująwszy mię za rękę, i dał mi przestrogę, żebym nie chodził drogą ludu tego, mówiąc:
12 “Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
Nie mówcie: Sprzysiężenie. Kiedykolwiek ten lud mówi: Sprzysiężenie, nie strachajcie się jako oni, ani się lękajcie.
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
Pana zastępów samego poświęcajcie; a on niech będzie bojaźnią waszą, i on strachem waszym.
14 Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
A będzie wam poświęceniem; ale kamieniem obrażenia i opoką otrącenia obydwom domom Izraelskim, sidłem i siecią obywatelom Jeruzalemskim.
15 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
I otrąci się wielu ich o nie, upadną i skruszeni będą, usidlą się a pojmani będą.
16 Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Zawiąż to świadectwo, zapieczętuj zakon między uczniami moimi.
17 Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
Tedy będę oczekiwał Pana, który skrył oblicze swoje od domu Jakóbowego, i poczekam go.
18 Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
Oto ja i dzieci, które mi dał Pan, są na znaki i na cuda w Izraelu, od Pana zastępów, który mieszka na górze Syon.
19 Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
A tak jeźliby wam rzekli: Dowiadujcie się od czarowników i od wieszczków, którzy szepcą i markocą, rzeczcie: Izali się nie ma dowiadywać lud u Boga swego? azaż umarłych miasto żywych radzić się ma?
20 Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
Do zakonu raczej i do świadectwa; ale jeźli nie chcą, niechże mówią według słowa tego, w którem niemasz żadnej zorzy.
21 Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
Dlaczego każdy z nich utrapiony i zgłodniały tułaćby się musiał; a będąc zgłodniałym, sam w sobie gniewać się będzie, i złorzeczyć królowi swemu, i Bogu swemu, w górę poglądając.
22 Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.
A gdy na ziemię spojrzy, oto ucisk i ciemność, zaćmienie, bieda, i obaczy, że jest wrażony do ciemności.

< Isaiah 8 >